BBC News, Yorùbá - Ìròyìn
Ìròyìn tó ṣe kókó
Kóòtù yọ̀ǹda ọkùnrin tó fi ìbálòpọ̀ pa ìyàwó rẹ̀, ariwo ta
Lọjọ Aje to kọja yii ni Adajọ Narendra Kumar Vyas, ti ile ẹjọ giga to wa ni Aarin-Gbungbun India, ni Chhattisgarh, yi idajọ 2019 pada, to si ni ki ọkọ iyawo naa maa lọ sile rẹ layọ ati alaafia.
Ẹbí Yetunde tí wọ́n rí òkú rẹ̀ nílé Àáfà Abdurahman n'Ilorin ń bèèrè ìdájọ́ òdodo
Ọjọ Ẹti ti ayajọ ololufẹ waye ni wọn ri oku Yetunde, eyi ti wọn sọ pe afurasi to ṣeku pa a ti ge wẹlẹwẹlẹ.
Èsì àyẹ̀wò òkú Abdulkadir Jimoh ti ṣàfihàn ohun tó ṣokùnfà ikú rẹ̀ ní àtìmọ́lé ọlọ́pàá n'Ilorin
Tẹ o ba gbagbe, Jimoh ku si atimọle ọlọpaa n'Ilorin l'ogunjọ oṣu kejila, ọdun 2024, lẹyin ti wọn mu un fun ẹsun pe o jẹ ọga rẹ, Gabriel Sunday, ni owo tiye rẹ jẹ N220,000.
Baálẹ̀ Esu ìlú Osogbo Kayode Esuleke wọ káà ilẹ̀ sùn
Kayode Eṣuleke dagbere faye ni ọjọ Karunlelogun osu kinni ọdun yii, oloogbe naa lo ọdun marundinlaadọrun-un loke eepẹ.
Fídíò, Karim Adeyemi, agbábọ́ọ̀lù ọmọ Naijiria tó ń ran àwọn ọ̀dọ́ lọ́wọ́, Duration 2,04
Adeyemi ṣalaye bo ṣe nifẹẹ orilẹede Naijiria lọkan to, to si fẹran lati maa ri awọn ọdọ orilẹede yii ti wọn ni ẹbun ere alafẹsẹgba naa.
'Mo lè kú láàárìn oṣù mẹ́ta pẹ̀lú bí Trump ṣe dáwọ́ ìrànwọ́ àjọ USAID dúró lórí oògùn ìtọ́jú àrùn HIV'
Ọkunrin kan,Mike Elvis Tusubira, ọmọ orilẹede Uganda to ni arun HIV to si n ṣiṣẹ ọkada wiwa, sọ pe ẹmi oun ko dè mọ.
Wọ́n ti lé akẹ́kọ̀ọ́ tó gé olùkọ́ rẹ̀ jẹ tó tún lù ú kúrò ní Yunifásítì
Atẹjade kan lati ọfiisi alukoro yunifasiti naa, Njelita Louis, fidi ẹ mulẹ, pe ọga agba ileewe yii, Joseph Ikechebelu, ti fi aṣẹ si ipinnu igbimọ to jokoo lori ọrọ naa, o si ti ni ki wọn le Precious kuro nileewe yii lẹyẹ-o-sọka.
Àwọn nǹkan mẹ́wàá tó yẹ kí o mọ̀ nípa àgbà ẹgbẹ́ Afenifere, Pa Ayo Adebanjo tó jáde láyé
Ní òwúrọ̀ ọjọ́, Ẹtì, ọjọ́ Kẹrìnlá, ọdún 2024 ni Adebanjo dágbére fáyé lẹ́ni ọdún mẹ́rìndínlọ́gọ́rùn-ún (96).
Kí ni ètò ààbò táwọn gómìnà ilẹ̀ Yorùbá kéde pé àwọn fẹ́ dá sílẹ̀?
Ìdásílẹ̀ ikọ̀ náà ló ń wáyé lẹ́yìn ọjọ́ mélòó kan tí àwọn àlùfáà ìjọ Aguda tí a mọ̀ sí 'Catholic Bishops' ní ìpínlẹ̀ Oyo pàrọwà sáwọn gómìnà náà láti fọwọ́sowọ́pọ̀, láti gbógunti bí àwọn agbébọn ṣe ń wọ ilẹ̀ Yorùbá.
Ìsìnkú Baálẹ̀ Èṣù, Kayode Eṣuleke, bẹ̀rẹ̀ l'Osogbo
Oloogbe Esuleke ti figba kan ri jẹ Kansilọ adugbo, oun si ni ẹni akọkọ to bura wọle sipo Kansilọ pẹlu lilo ada ati ìbọn.
Orin, Kò ṣeé má gbọ̀ọ́, Duration 0,54
Akojọpọ iroyin Naijira ati kaakiri agbaye
Fídíò, Odò yípadà di odò ẹ̀jẹ̀, wo ìdí abájọ, Duration 0,42
Gẹgẹ bi araalu naa to wa ninu fidio yii ṣe ṣalaye fun BBC, o ni awọn kan ni wọn dana sun ilẹ ni kutukutu owurọ.
Ìròyìn Àkàgbádùn
Àwọn ẹ̀ṣọ́ ààbò kún àwọn ìjọba ìbílẹ̀ fọ́fọ́ ní Osun, ìbẹ̀rù bojo gbọkàn àwọn òsìṣẹ́
Ọpọ awọn oṣiṣẹ ni ko mọ odo ti wọn maa da ọrunla, ti ibẹrubojo si gba ọkan wọn nitori wọn ko mọ eyi to maa jẹ ṣiṣe paapaa bawọn alaga naa ṣe ni awọn ti ṣetan loati gba ipo awọn pada.
Iléeṣẹ́ epo Shell kọtí ọ̀gbọin sí ìkìlọ àwọn tí epo ń ba agbègbè wọn jẹ́
Onwoye kan ṣapejuwe eto atunṣe yii bii jibiti, eyi to ti fi ọpọ owo ṣofo, to si ti da awọn eeyan ilẹ Ogoni sinu iṣoro epo to n ba nnkan jẹ fun wọn.
Á bẹ̀rẹ̀ ìkọlù padà tí Hamas kò bá tú gbogbo ọmọ Israel tó wà ní ìgbèkùn rẹ̀ sílẹ̀ títí Sátidé - Netanyahu
Aarẹ Donald Trump ni Hamas gbọdọ tu awọn ọmọ Israel to jigbe ni Gaza silẹ titi ago mejila ọsan ọjọ Abamẹta to n bọ, bi bẹẹ kọọ, Israel gbọdọ ṣina bolẹ.
Ikọ̀ agbébọn tuntun fi ìdí ibùba rẹ̀ kalẹ̀ sí Zamfara
Akojọpọ awọn agbebọn tuntun yii ni wọn n ṣiṣẹ ikọlu pọ, bi awọn araalu ṣe wi.
Wo àwọn orílẹ̀èdè tó léwájú nínú ìwà àjẹbánu ní àgbáyé lọ́dún 2024
Awọn amoye naa pin awọn orilẹede si isọri, ti wọn si fun wọn ni maaki bẹrẹ lati odo si ọgọrun un.
Ta a ni Natasha Osawaru, tí 2face Idibia kéde pé òun fẹ́ ẹ́ fẹ́?
Ni bi ọsẹ diẹ sẹyin ni 2face kede pe oun ati iyawo rẹ, Anni Idibia ti fopin si igbeyawo wọn.
Akẹ́kọ̀ọ́ Poly Ibadan mẹ́wàá dèrò iléèwòsàn lẹ́yìn tí wọ́n fa gáàsì olóró símú
Ohun ti a gbọ ni pe lẹyin ti awọn ọmọ naa ti wọn jẹ akẹkọọ ẹka ti wọn ti n kọ nipa ayẹwo ẹjẹ; 'Department of Science Laboratory Technology' (SLT), pari idanrawo ranpẹ ni wọn lugbadi afẹfẹ oloro naa.
Àlàyé rèé lórí bí ATM yóò ṣe máà já àlékún owó tí oníbàárà bá gbà èyí tí CBN ṣẹ̀ṣẹ̀ gbé jáde
Ní ọjọ́ Kìíní, oṣù Kẹta, ọdún 2025 ni jíjà owó náà yóò bẹ̀rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìròyìn náà ṣe sọ.
Ìyà tí ẹ̀gbọ́n bàbá mi fi jẹ mí ní kékeré ló sọ mí di aláàbọ̀ ẹsẹ̀, ẹrù àrùwọrùn ni kò jẹ́ kí ń ga - Ìyá Gbonkan
Iya Gbonkan, ti i se ọmọbibi ilu Otu nipinlẹ Oyo, ti iya rẹ si jẹ ọmọ ilu Iseyin, ni ipenija pọ loriṣiriṣii lẹnu iṣẹ tiata, o ni diẹ loku ki ipenija ọhun mu ẹmi oun lọ.
'A ti ṣetán láti gba ipò wa padà bí ilé ẹjọ́ Kòtẹ́milọ́rùn ṣe ti dáwa láre'
Ile ẹjọ paṣẹ pe ki gbogbo alaga ijọba ibilẹ ti wọn jẹ ọmọ ẹgbẹ oṣelu APC pada sipo gẹgẹ alaga ijọba ibilẹ koowa wọn.
'Omi nìkan la mu fún ọjọ́ márùn-ún gbáko lákàtà àwọn Ajínigbé'
Amọtẹkun Ipinlẹ Ondo tun fi panpe ọba mu awọn afurasi ọdaran ogun, to fi mọ awọn ajinigbe ati awọn darandaran ti wọn fi ipa ba iya agba ẹni ọdun mẹrindinlọgọrin lopọ lasiko to n lọ oko niluu Ifira Akoko.
Ìròyìn Pàtàkì
Kọ́milẹ́kọ̀ọ́
Ẹ tẹ̀lé wa lórí ìkànnì ayélujára
Móríwú
Ìwádìí kíkún lóríi kókó ìròyìn
Ṣé mìmì kankan ń mi APC bí Atiku, Obasanjo àtàwọn àgbà òṣèlú míì ti ń ṣèpàdé kiri?
Bi o tilẹ jẹ pe ko sẹni to mọ ohun ti awọn ipade yii n da le lori amọ awọn onwoye ni kuru-kẹrẹ awọn oloselu ko le sẹyin eto idibo lọ.
Portable sọ̀kò ọ̀rọ̀ sí bàbá rẹ̀, ka ọ̀pọ̀ ẹ̀sùn sí i lọ́rùn pé bàbá burúkú ni
Portable bọ sori ikanni ayelujara Instagram rẹ lati fẹsun kan Baba to bi lọmọ pe o lu oun ni jibiti, to si fi silẹ lasiko to n koju iṣoro.
Kí ló dé tí Nnamdi Kanu fàbínú yọ níbi ìgbẹ́jọ́ rẹ̀?
Kanu bu ẹnu atẹlu bi ileẹjọ se n fi igbẹjọ rẹ kalẹ, to si fẹsun kan wọn pe wọn yii idijagbara rẹ fun idasilẹ orilẹede Biafra si ẹsun igbesunami.
Adelabu ṣèpàdé pẹ̀lú IBEDC lórí ìdákúrekú iná mọ̀nàmọ́ná ní UCH
Iroyin kan to n ja lori ayelujara ni ọpọlọpọ àwọn alaisan to n gba itọju nile iwosan UCH lo n la isoro alagbara kọja tori àìsí ina ọba.
Kí ni Facebook ṣe fún Femi Falana, tó fi wọ́ Meta lọ sìlè ẹjọ̀?
Falana ni bi Facebook se lo aworan rẹ tako ofin ẹtọ ọmọniyan labẹ ofin ọdun 1999.
Iṣẹ́ Káfíńtà ni mo kọ́ níbẹ̀rẹ̀ ayé mi, àmọ́ mo ń pá tó N20m láàrin ọ̀sẹ̀ kan lórí Tiktok - Peller
Hebeeb Hamzat, ẹni ti ọpọ mọ si Peller, sọ eyi fun ileeṣẹ iroyin abẹle Channels lasiko ifọrọwerọ kan to se, to si jẹ ko di mimọ pe iṣẹ Kapẹnta ni oun kọ saaju ko to di ilumọka.
Mount Zion tún pàdánù òṣèré míì nínú fíìmù Abbattoir lẹ́yìn Baba Gbénró
Ìyàlẹ́nu sì lo jẹ fún ọpọlọpọ olólùfẹ́ sinima Abbattoir láti gbọ́ ni ọ̀sàn ọjọ́ Aiku pé gbajumọ osere miran nínú sinima náà, Flora, naa tún ti dagbere fáyé.
Ó yẹ káwọn ètò ìṣèṣe kan ṣáájú kí Ọba tó dá Olóyè dọ̀bálẹ̀ níta gbangba tó fojú balé ẹjọ́ - Ààrẹ ẹgbẹ́ Yorùbá YCW
Aarẹ ẹgbẹ YCW, Dotun Hassan, sọ pe ọrọ to ṣẹlẹ yìí ati bi kabiyesi Abdulsemiu Ogunjobi ti dero ile ẹjọ le lẹyin fun Orile Ifo.
Princess ké gbàjarè, káfíntà tó fipà bá ọmọ ọdún mẹ́sàn-án lò pọ̀ l'Ekoo di èrò ẹ̀wọ̀n
Nipa bi ẹjọ naa ṣe de kootu, ajafẹtọọ ọmọniyan, Damilola Adekoya ti awọn eeyan mọ si Princess, lo fi iṣẹlẹ naa lede bo ṣe ṣẹlẹ.
Ààrẹ àkọ́kọ́ ní Namibia, Sam Nujoma jáde láyé
Nujoma ló jà fún òmìnira Namibia lọ́wọ́ South Africa lọ́dún 1990 lẹ́yìn tó dá ẹgbẹ́ South West Peoples' Organisation (Swapo) lọ́dún 1960.































































