Boko Haram: Ẹ̀mí kan bọ́, èèyàn 16 míì farapa nínú ìṣẹ̀lẹ̀ àdó olóró ní Maiduguri

Oríṣun àwòrán, @___FAREED
Aifararọ ati idarudapọ waye nilu Maiduguri, tii se olu ilu ipinlẹ Borno lasiko ti ọpọ eeyan n se ọdun Ileya.
Bi o tilẹ jẹ pe lọjọ Ileya, o yẹ kawọn olugbe ilu naa maa fọkan balẹ jẹran ọdun wọn ni, amọ ojo ado oloro lo n rọ leralera nilu naa, bẹrẹ lati ọjọ Ẹti.
A gbọ pe eeyan mẹrindinlogun lo ti ba isẹlẹ naa rin, ti ẹmi kan si bọ sinu rẹ pẹlu, nigba ti awọn olugbe ilu naa n sa kiri lati sa asala fun ẹmi wọn.
Nigba to n fidi isẹlẹ naa mulẹ, Kọmisana ọlọpaa nipinlẹ Bornu, Mohammed Aliyu ni igba mẹta ni ado iku dun gbamu nilu naa.
Aliyu sọ fun ileesẹ akoroyinjọ nilẹ wa, NAN pe agbegbe mairi, Custom ati Gwange to wa nilu Maiduguri ni wọn ti gbọ ibugbamu awọn ado iku naa.
Oríṣun àwòrán, @___FAREED
"A ti ran awọn osisẹ wa to mọ nipa ado oloro lọ sagbegbe naa lati se tọpinpin isẹlẹ naa. Bakan naa ni wọn wa nile iwosan ti wọn ko awọn eeyan to farapa lọ."
Ni bayii, alaafia ti n pada jọ̀ba nilu naa, ti awọn agbofinro si ti n sa ipa wọn lati dena isẹlẹ ibugbamu awọn ado oloro naa.
Bi o tilẹ jẹ pe a ko tii lee sọ ohun to sokunfa isẹlẹ naa tabi awọn to wa nidi rẹ, amọ awọn eeyan ni o see se ko jẹ ikọ agbesunmọmi Boko Haram lo n se ọsẹ naa.
Oríṣun àwòrán, @___FAREED
Bẹẹ ba gbagbe, ọjọbọ ni iroyin gbalẹ kan pe, awọn ọmọ ikọ mujẹmujẹ naa kọlu gomina ipinlẹ Borno, Zullum, ti wọn si se awọn ẹsọ alaabo rẹ lese.
Amọ a gbọ pe ori ko gomina naa yọ.
Àwọn alákatakítí pa ènìyàn 19 ní Borno
Oríṣun àwòrán, AFP
Ikọlu yi n waye lẹhin ti ile isẹ ọmọogun orilẹede Naijiria ti figa gbaya wipe awọn ti bori Boko Haram.
O kéré tan ènìyàn mọ́kàndínlọ́gbọ̀n ló ti pàdé ọlọjọ wọn níbi ìkọlú ti àwọn Boko Haram tun ṣe ní ìlú kan ní Maiduguri lánà òde yìí.
Gẹ́gẹ́ bí ọkan lára àwọn tórí kọ́yọ nínú ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣe sọ, Abatcha Umar àwọn okú tí òun rí kà tó mọkàndílogun tó fi mọ àbúrò òun nàá.
Ìṣẹ̀lẹ̀ náà jẹ́ ọkan lára àwọn ikọlu to tún buru níní àwọn èyí tó tí ń wáye, èyí to fi han pé ìjọba oríẹ̀-èdè Nàìjíríà.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
Awọn ikọ Boko Haram náà kọlu ìlú Mailari ní agbègbè Guzamala ní ìpínlẹ̀ Borno
Ọ̀kan lára àwọn òṣìṣẹ́ ajà fẹ́tọ̀ọ́ ní àgọ́ àwọn ogunlende tó gba àwọn tí orí kó yọ sàlàyé pé àwọn to kú tó mẹ́tàlélọgọ́ta.
Umar fi kun ọ̀rọ̀ rẹ̀ pé àwọn ti ń kófìrí ikọ̀ Boko Haram ní àgbègbè náà ní ọjọ́ mẹ́ta sí ìgbà ti ìṣẹ̀lẹ̀ náà wáyé.
Awọn ará ìlú ti rọ ìjọba láti fi àwọn ọmọogun sí ìlú to sún mọ wọn Gudumbali kí ìkolù yìí tó wáyé sùgbọn ti wọn kò kọ bi ara sí ẹ̀bẹ̀ náà.
Òṣìṣẹ́ ajàfẹtọ tó wà níbl sàlàyé pé ẹgbẹ̀lẹ́gbẹ̀ àwọn ará ìlú ló ti sá wá si àgó ogunléndé tí òun ti ń ṣiṣẹ́ ni Monguno.
Boko Haram kọlu abule Kofa ni Maiduguri
O kere tan eniyan kan ti padanu ẹmi ti ọpọlọpọ miran si ti f'arapa ninu ibugbamu ikọlu Boko Haram n'ipinlẹ Borno.
Iroyin ti o tẹ wa lọwọ sọ wi pe awọn agbesunmọmi Boko Haram kọlu abule Kofa ti o wa ni adojukọ ibudo ifiniwọsi fun awọn ti isẹlẹ ṣi nipo ti Dalori n'ilu Maiduguri loru anọ.
Agbẹnusọ fun ajọ alakoso isẹlẹ pajawiri (sema) ti ipinlẹ Borno, Bello Dambatta fi idi ikọlu yi mulẹ pẹlu alaye wipe ogunlọgọ awọn eniyan miran ni wọn fi ara pa nigbati awọn agbesunmọmi Boko Haram ju inọ si awọn ile lorisirisi ninu abule naa.
Ikọlu yi n waye lẹhin ti ile isẹ ọmọogun orilẹede Naijiria ti figa gbaya wipe awọn ti bori Boko Haram.
Olori ikọ Operation 'Lafiya Dole', Rogers Nicholas sọ eyi nibi ìfilọ́lẹ̀ ikọ̀ ọmọ ogun apapọ orilẹede Naijiria ati orilẹede Cameroon ni ilu Maiduguru lọjọ aiku.

'A ti pa Boko Haram run patapata' - Ọmọogun
Ikọ̀ ọmọ ogun ilẹ Naijiria sọ nini ifilọlẹ apapọ ọmọ ogun orilẹede Naijiria ati Cameroon pe awọn ti sẹgun Boko Haram ni àsẹ́wọlẹ̀