May 27: Nàìjíríà se Àyájọ́ ọjọ́ àwọn èwe

Àwọn èwe Nàìjíríà

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Àkọlé àwòrán,

Àyájọ́ ọjọ́ àwọn èwe lónìí

Ẹ̀rín ẹ̀ẹ̀kẹ́ àwọn èwe a máa mú 'nú ẹni dùn, ojú wọn bíi ti Ángẹ́lì a sì máa gbilẹ̀ nínú ọkàn ẹni.

Àyájọ́ ọjọ́ àwọn èwe lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà jẹ́ ọjọ́ tí wọ́n yà sọ́tọ̀ láti pọ́n àwọn èwe lé.

Ọjọ́ kẹtàlélógún, osú kárùn-ún, ọdún 1964 ni orílẹ̀-èdè Nàìjíríà kọ́kọ́ se ayẹyẹ àyájọ́ ọjọ́ àwọn èwe.

Oríṣun àwòrán, STEFAN HEUNIS

Àkọlé àwòrán,

Àyájọ́ ọjọ́ àwọn èwe lónìí

Lọ́dún tó kọja, ààrẹ́ Muhammadu Buhari ní a gbúdọ̀ ríi dájú wí pé àbò wa fún àwọn èwe Nàìjíríà.

Àkọlé fídíò,

'Àsìkò Amojúẹ̀rọ Seyi ni ló fi wọlé l'Oyo, kìí ṣe àsìkò èmi Omobolanle'

Láti ìgbà náà ni ìjọba ti ya ọjọ́ náà sọ́tọ̀ fún síse àyájọ́ ọjọ́ àwọn èwe àti yíyẹ́ wọn sí láì ya ọmọ kan sọ́tọ̀.

Oríṣun àwòrán, PHILIP OJISUA

Àkọlé àwòrán,

Àyájọ́ ọjọ́ àwọn èwe lónìí

Ní ọjọ́ ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni oníkálùkù orílẹ̀-èdè àgbáyé máa ń se ayẹyẹ àyájọ́ ọjọ́ àwọn èwe káàkiri àgbáyé.

Àkọlé fídíò,

'Nígbà tí mò ń wà Awolowo, Gowon, Babangida, mo fi ara mi sípo ọ̀wọ̀ tóri ...'

Ọdún 1955 ni wọ́n kọ́kọ́ se àyájọ́ yìí lágbayé lábẹ́ onígbọ̀wọ́ àjọ́ àgbáye kan tó ń rí sí ìtọ́jú àwọn èwe, International Union for Child Welfare ní Geneva.

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Àkọlé àwòrán,

Àyájọ́ ọjọ́ àwọn èwe lónìí

Ní ọdún 1954 ni ìpàdé ìgbìmọ̀ àjọ ìsọ̀kan àgbáyé kéde rẹ̀, wọ́n se ìfilọ́lẹ̀ rẹ̀ kí gbogbo orílẹ̀-èdè lè yan ọjọ́ kan fún ti wọn.

Àkọlé fídíò,

Olusegun Obasanjo: Ọmú ìyá mi ti mo fi ń mùkọ ni kekere ló jẹ ki ń lókun

Lákọkọ́, wọ́n se ìfilọ́lẹ̀ rẹ̀ láti se ìmúgbòòrò ìgbọ́ra-ẹni-yé láàrín àwọn èwe.

Ẹ̀ẹ̀kejì, láti bẹ̀rẹ̀ ìgbésẹ̀ fún jíjẹ ànfàní àti síse ìtọ́jú àwọn èwe lágbayé.

Awọn iroyin miran ti ẹ le nifẹ si:

Àkọlé fídíò,

Asa Trokosi nibi ti ọmọde ti n jiyan ẹsẹ mọlẹbi rẹ , wọpọ ni Ghana, Togo ati Benin.