June 12: Àwọn Ẹgba àti Owu ní ojúṣe Abiola yọ sílẹ̀ lẹ́yìn ọ̀pọ̀ ọdún tó jáde láyé
Ilé Ààrẹ tí Abiọla ń kọ́ lọ l'Abẹokuta ti di ọgbà wèrè báyìí.
Moshood Kashimaawo Olawale Abiola ni wọn bi nilu Abẹokuta nipinlẹ Ogun lọdun 1937.
O díje fun ipo aarẹ lọdun 1993 pẹlu Babagana Kingibe gẹgẹ bii igbakeji rẹ níní idibo ti àwọn eniyan Naijiria gba pe o dara julọ.
Iku ba ọla Abiola jẹ́
L'ọdun 1994 lo kede ará rẹ gẹgẹ bii aarẹ Naijiria ni eyi ti wọn fi fi Abiọla satimọle nibi to ti pada jẹ Olorun nipe.
MKO ku ni ọjọ keje, oṣu keje, ọdun 1998 satimọle.
Aarẹ Mohammadu Buhari fi oye Naijiria to ga julọ (GCFR) da Abiọla lọla lọjọ kejila, oṣu kéfa, ọdun 2018 yii.
Buhari fun Abiola ni oye GCFR to ga julọ ni Naijiria lọdun 2018
Àwọn olùkòpá nínú ìdìbò June 12 1993 sọ ọ́ di mímọ̀ pé ó jẹ́ ìgbà àkọ́kọ́ tí ìdìbò lọ déédé láàrin Hausa, Igbo àti Yorùbá.
Ki Abiọla to ku lo ti n kọ ile Aarẹ si Abẹokuta eyi to ti di àkọ́tì bayii.
MKO Abiọla, ọ̀pọ̀ eniyan lo n ṣelédè lẹyin rẹ
Ikú Abiọla ni ọpọlọpọ gba pe kìí ṣe àmúwá Ọlọrun rara nitori pe wọn ni wọn paá satimọle ni.
Awọn ènìyàn Naijiria kò lè tètè gbagbe Baṣọrun Kashimaawo Olawale Abiọla fún iṣẹ ribiribi to ṣe silẹ ki ọlọjọ to de.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Àwọn asọni di Òtòṣì àti Aláìmọ̀kan là ń bá jà - Tinubu
- Wo ohun tó mú kí àyájọ́ June 12 ṣe pàtàkì fún Nàíjíríà
- ₦324bn la pín fún 136,000 oníṣòwò ké kè ké lásìkò ìgbélé Covid-19 - Buhari
- Wo ibi tí ìpalẹ̀mọ́ fún ìwọ́de June 12 dé dúró ní Nàíjíríà àti òkè òkun
- Ọ̀rọ̀ díẹ̀ ati ìgbésẹ̀ akin lá máa gbé báyìí lórí ọ̀rọ̀ Nàíjíríà - Obasanjo
- Wo ipa mánigbàgbé táwọn ààrẹ ní sáà ìjọba alágbádá kẹ́rin ṣe
- Wo àwọn ààrẹ alágbádá tó ti jẹ ní Nàìjíríà láti 1960 di àkókò yìí
- MKO Abiola, iṣẹ́ aṣẹ́gità ló fi bẹ̀rẹ̀ okoòwò