Baba Suwe: Ó lé ní ọdún méjì tó fi sàìsàn láì kópa nínú tíátà

Oríṣun àwòrán, Babasuwe_official instagram
Odu ni Babatunde Omidina , ti ọpọ eeyan mọ si Baba Suwe ni agbo ere tiata, kii si se aimọ fun oloko.
Baba Suwe ni ọpọ eeyan mọ si adẹrinposonu, to si tun maa n da awọn eeyan laraya fun spọlọpọ ọdun.
Sugbọn niwọn igba to se pe atori ;aye, to ba lo siwaju, a tun lo sẹyin, iriri aye kan sọ Baba Suwe si adanwo, eyi to mii logbologbo.
Iriri aye yii si lo da lori bi awọn aṣọbode nilẹ wa se mu ni papakọ ofurufu pe o pe oogun oloro Cocaine.
Wahala de ba gbajumọ osere tiata yii, ti oju rẹ si ri mabo ni ahamọ awọn asọbode.
Rọ ọhun di ile ẹjọ, bi o tilẹ jẹ pe gbogbo iyanju awọn asọbode nigba naa pe ko su oogun oloro ọhun mọ igbẹ lo ja si pabo.
Flood: Ọ̀pọ́ Dúkìá ló sọnù ní 2019 lásìkò tí ìjọba ṣí ’dáàmù Ọyan’
Asẹyinwa, asẹyinbọ, ile ẹjọ da Baba Suwe lare, to si ni ki ileesẹ asọbode ilẹ wa lọ san owo gba, ma binu fun.
Bi o tilẹ jẹ pe ko ri owo naa gba titi di oni, sibẹ lẹyin iriri yii si tun ni aisan de ba ilumọọka osere tiata naa, to si dubulẹ aisan.
Okiki kan kari aye pe ojojo n se ogun Baba Suwe, ara ogun ko le, ti awọn ẹlẹyinju aanu si dide iranwọ lati doola ẹmi rẹ lọwọ iku ojiji.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ojú Shagbada Erigga rèé lẹ́yìn tó pa ọ̀rẹ́bìnrin rẹ̀ l'Akinyele ní Ibadan
- Ìdí tí lílọ Yúrópùù fi di èèwọ̀ fún Nàìjíríà àti àwọn orílẹ̀-èdè adúláwọ̀ míì
- Arúfin ni Seyi Makinde pẹ̀lú bó ṣe gbà kí wọ́n sin Ajimobi sí GRA - Amòfin
- Ṣé ó leè jẹ́ ilẹ̀ tí Makinde kò jẹ́ kí Florence Ajimobi gbà ló ń bi nínú?
- Akinyele tún gbàlejò àwọn mùjẹ̀mùjẹ̀, tìyá-tọmọ̀ fara gbọgbẹ́
- Ẹ pèsè ẹlẹ́rìí púpọ̀ bí bẹ́ẹ̀ kọ́, Sotitobire yóò jẹ́rìí fúnrarẹ̀ o! - Ilé ẹjọ́ ìpínlẹ̀ Ondo
- Ilé ìwòsàn kan rèé tó ń fi àtùpà gbẹ̀bí aláboyún
Wọn gbe adẹrinposonu naa lọ soke okun, ti lọrun si gbọ adura rẹ, amọ lati bii ọdun meji to ti pada de orilẹ ede yii, Baba Suwe ko kopa ninu ere tiata kankan.
Sugbọn iroyin to wa n tẹ wa lọwọ bayii ni pe ba oke ti da alaafia pada si agọ ara Baba Suwe, to si ti pada si ẹnu isẹ tiata bayii.
Ninu aworan to fi sita loju opo Instagram rẹ, babasuwe_official, ibẹ lo ti kede pe oun ti wa ni ẹnu isẹ ere tiata pada.
Oríṣun àwòrán, Google
Ọ̀pọ̀lọ̀pọ̀ àwọn olósèré ló ti ń tọrọ àánú láti ọwọ́ àwọn ọmọ Naijiria láti lè fi tójú Baba Suwe tó ń se àìsàn.
O kede pe akọle ere ti oun n ya ni Adigun ọga ọga, ti aworan naa si se afihan rẹ to wọ asọ ọlọpaa.
Bakan naa ni Adewale Akorede taa mọ si Okunnu ba wọ asọ ọlọpaa naa, ti Mr Latin si duro si aarin wọn.
Awọn ololufẹ Baba Suwe si lo n ki ku oriire loju opo rẹ naa, bẹẹ ni wọn n gbadura pe ogun to sẹ fun-un, ko ni gberi mọ laelae.
A wa n gbadura pe ajinde ara yoo maa jẹ fun Baba Suwe, ko si ni wolẹ aisan mọ titi aye.
Gbajúgbajà òṣèré tíátà, Baba Suwe ń ṣe àìsàn
Saaju la ti mu iroyin wa fun yin pe lẹyin ti iroyin jade wi pe Baba Suwe n se aisan, awọn akẹẹgbẹ rẹ ti kesi awọn ọmọ Naijiria lati dide iranwọ si Baba Suwe.
Awọn olosere Nollywood naa gbadura fun iwosan rẹ lori ero ikansiraẹni Instagram wọn.
- Ṣẹ gbọ́ nípa Alájọ Ṣómólú, tó ta mọ́tò ra kẹ̀kẹ́?
- Yorùbá dùn lédè, ẹ máa sọọ́
- Ẹfunroye Tinubu - Ògbóǹtagí oníṣòwò, olówò ẹrú àti afọbajẹ
- Samuel Ajayi Crowther, òjíṣẹ́ Ọlọ́run tó gbé èdè Yoruba lárugẹ
- Mọrèmi Àjàṣorò, akọni obìnrin tó gba Ilé Ifẹ̀ sílẹ̀ lóko ẹrú
- Ọ̀rọ̀ǹpọ̀tọ̀niyùn, Aláàfin obìnrin àkọ́kọ́ rèé, tó ní nǹkan ọkùnrin
BBC Yorùbá: Temidayọ Ọlọfinsawo ní kò rọrùn láti darí òṣìṣẹ́ ọlọ́pọlọ pípé
Yomi Fabiyi gboriyin fun Baba Suwe fun ipa ribiribi to ko ninu igbesi aye rẹ ati bi o se da olokiki eniyan ninu isẹ osere.
Bakan naa ni wọn kesi Ile Isẹ to n gbogun ti lilo ogun oloro lorilẹede Naijiria, NDLEA lati da miliọnu mẹẹdọgbọn rẹ ti o yẹ pada fun lẹyin ọdun mẹjọ ti wọn ti fẹsun kan Baba Suwe wi pe o gbe ogun oloro cocaine, amọ ti gbogbo iwadii fihan wi pe ko se bẹẹ.
Osu Kẹjọ, ọdun 1958 ni wọn bi Baba Suwe ni agbegbe Inabere ni ilu Eko ni ijọba ibilẹ Ikorodu, ko to di wi pe o bẹrẹ isẹ osere ni ọdun 1972 pẹlu fiimu rẹ, Ọmolasan ti Obalende se agbatẹru fun.