Babajide Sanwo-olu: Mo ti fi ọgbọ̀n ọdún ṣe iṣẹ́ púlọ́mbà

Oríṣun àwòrán, Twitter/Sanwo-Olu
Yoruba bọ, wọn ni ki ọrọ to o dayọ, oju a ri.
Lo difa fun gomina ipinlẹ Eko, Babajide Sanwo-olu to sọ pe oun naa ti ṣe iṣẹ pulọmba ri ni bi ọgbọn ọdun sẹyin.
Gomina o deede si aṣọ loju ọrọ yii o, ọrọ ni n ba moko-moro wa.
- Adà ní bàbá mí yọ sí mí nígbà tí mo ní mò fẹ̀ máà kọrin-Popular Jingo
- Èèyàn 111 ní àrùn Coronavirus tún ṣẹ̀ṣẹ̀ ràn ní Nàìjíríà ní Ọjọ́ọ̀rú
- Ìtumọ̀ àbàdòfin lórí omi tí ìjọba tẹramọ́ tó n bí àwọn ọmọ Nàìjíríà nínú rèé
- Ẹ dín iye ìgbà tẹ n gorí obìnrin kù torí ìdìbò tó n bọ̀, kẹ́ẹ lè lágbára láti ṣe ... - Ọ̀gá àgbà ọlọ́páà
Gomina Sanwo Olu sọ ọrọ yii níbi ayẹyẹ ikẹkọọ jade awọn akẹkọọ 6,252 to kọ iṣẹ ọwọ ni awọn ibudo ikọsẹ mejidinlogun to jẹ ti ijọba nipinlẹ naa.
Sanwo-olu gba awọn ọdọ ati awọn obinrin ni imọran, lati gbaju mọ isẹ ọwọ, dipo kii wọn o ma a reti pe iṣẹ yoo jade lati ọdọ ijọba tabi ileesẹ aladani.
Ko tan sibẹ o, Sanwo-olu rọ awọn akẹkọọ jade naa, lati lo anfaani isẹ ti wọn kọ, fi sọ ara wọn di ẹni to n gba eeyan si iṣẹ.
O tun rọ wọn lati tubọ ma a wa imọ kun imọ l'ẹnu isẹ wọn.
- Wo iye ìgbà tí ẹgbẹ́ òṣìṣẹ́ àtàwọn ọmọ Nàìjíríà ti ṣèwọ́de lórí àfikún owó epo bẹntírò
- Wo nkan tó yẹ kí o mọ̀ nípa ààrùn SC tí Laycon BBNaija sọ pé òun ní.
- Wo ìlànà tí ìjọba Saudi Arabia fi síta fún Umrah tí yóò bẹ̀rẹ̀ padà l'óṣù Kẹwàá
- Ìjàmbá iná pa èèyàn 23, tó fi mọ ọmọ iléèwé àlákọ́bẹ̀rẹ̀ ní Lokoja-Abuja
Awọn isẹ ọwọ bi i irun ṣiṣe, ṣíṣe ara loge, oúnjẹ sise, imọ kọmputa, irun gige, bàtà ṣíṣe, aṣọ rírán, ati awọn miran.
Kọmisanna fun ọrọ awọn obinrin ati fifi opin si óṣi nipinlẹ Eko, Cecilia Dada sọ pe iwe ẹri ti yoo fun awọn akẹkọọ naa ni anfaani lati wọ ileewe ijọba ipinlẹ naa, ti wọn ti n kọ isẹ ọwọ ni wọn yoo fun wọn.