Olamide Ogunade Charcoal artist: Bí mo ṣe ń lo ẹrọ ayélujára fi ran títa àwòrán mi lọ́wọ́
Olamide Ogunade jẹ ọdọ amọ o tun da yọtọ larin awọn ọdọ fun iru iṣẹ ọwọ ara ọtọ to n ṣe.
O jẹ eeyan to maa n ronu tayọ nkan ti oju n ri eyi to si maa n fi awonran rẹ ṣalaye fun awọn eniyan.
Lati kekere ni Olamide ti ri ẹbun yii ninu ara rẹ to si jara mọ ọ lai ṣe iye meji.
Oríṣun àwòrán, Olamide Ogunakin
"Iṣẹ ọna ni ṣe pẹlu wiwa ọna ati ba awọn eeyan sọrọ, mo maa n woye kikun aworan gẹgẹ ọ̀rọ̀ sisọ laarin rẹ ati eeyan to n wo aworan naa".
Iwuri ni iṣẹ aworan yiya Olamide yii to si ni o ti gbe oun jade kuro lorilẹede Naijiria lọ si Dubai amọ ọja ọhun naa ko ya lorilẹede Naijiria.
O mẹnu ba ipa ti ayelujara n ko ninu tita ọja rẹ gẹgẹ bi eyi to dara gidi.
Iyalẹnu ni wipe ikọwe pencil ati eedu ni Olamide fi n ya awọn aworan rẹ.
Olamide naa gẹgẹ bi ọdọ Naijiria tẹnu mọ ọ pe ọrọ oṣelu ati ipo ti ọrọ aje Naijiria wa jẹ ọkan lara ohun to n ṣakoba fun iṣẹ rẹ.
- Ìdìbò ọdún 2023 leè má wáyé bí ìjọba kò bá yanjú ìpèníjà ààbò - Akeredolu
- Ẹnikẹ́ni tó bá fa wàhálà míì lẹ́yìn rògbòdìyàn ọ̀rọ̀ Hijab tó wáyé n'Ilorin yóò fojú winá òfin - AbdulRazaq
- Ẹ̀yà Yorùbá ti fara ṣiṣẹ́ púpọ̀ fún Naijiria, nítorí nàá à kò le déèdé sọ pé a fẹ́ kúrò - Àgbààgbà Yorùbá
- Sùkẹ̀! Ọ̀rọ̀ òṣèlú ni gbogbo ẹ tí Akeredolu ṣe tako ìdásílẹ̀ Oduduwa Nation - Banji Akintoye