Ooni: Ayẹyẹ ọdún Moremi yóò wà fún ìtẹ̀síwájú àwọn obìnrin

Ọ̀ọ̀ni Ilẹ̀ Ifẹ̀

Oríṣun àwòrán, ooniadimulaife

Àkọlé àwòrán,

Ọ̀ọ̀ni Ilẹ̀ Ifẹ̀ n gbaradi de ọdun Mọremi

Ọọni ti Ile -Ife, Ọba Adeyẹye Ogunwusi, Ọjaja Keji ti fẹ ṣe afihan orin kikọ ati ere itage lati bu ọla fun Olori Moremi Ajaṣoro to ja fun ominira awọn ẹru nigba aye rẹ.

Aṣoju aṣa fun Olori Moremi, Ọmọọba Ronke Ademiluyi lo fi igbesẹ yii lede ni ipo Ọba Adeyeye Ogunwusi.

Ọmọọba Ademiluyi ni pe ere itage ati orin kikọ ti yoo jẹ oni wakati kan ataabọ fun ọjọ mẹtala naa, ni yoo waye ni Osu Kejila ni Ilu Eko.

Àkọlé fídíò,

Ìnú mi kìí dùn nígbà trí mo ń ṣiṣẹ́ ni bánkì tó ìgbà ti mo bẹ̀rẹ̀ mẹkáníìkì

O fikun un pe abajade ere itage naa yoo wa fun ṣiṣe iranwọ fun awọn obinrin ti wọn ti fi ṣe ẹru lọna igbalode.

'Àwọn èèyàn ń fi orúkọ mi lu àwọn obinrin ní jìbìtì'

Ọọni ile ifẹ ni oun ti fi ọrọ arabinrin ti o n kede pe oun ati aṣiwaju ọbalaye naa ni adehun ifẹ ki o to fẹ Olori rẹ ni aipẹ yii to ọlọpaa leti.

Àkọlé fídíò,

Ooni: Mo ti fi ọ̀rọ̀ obinrin tó ń parọ́ ìfẹ́ mọ́ mi sun agbófinró

Arabinrin Elizabeth Ọdunlami ni okiki kan lori iroyin kan to fi si ori itakun facebook rẹ pe oun ati Ọọni ni adehun lati fẹ ara wọn pẹlu ẹsun pe kabiyesi naa ti fi orukọ oun ṣe ọpọlọpọ idundura okoowo.

Ọrọ Elizabeth Odunlami loju opo Facebook.

Amọṣa, Ọọni ile ifẹ, Adeyẹye Ogunwusi ni ko sohun to jọ eyi ati pe awọn onijibiti kan ni wọn n lo orukọ oun lati lu awọn obinrin ni jibiti.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

O ni oun ti fi ọrọ naa to awọn agbofinro leti.

Ninu ọrọ to ba BBC News Yoruba sọ, agbẹnusọ fun Ọbalaye naa, Moses Ọlafare ni ninu ko jẹ wi pe awọn onijibiti lo ti kan arabinrin naa lara abi ko jẹ pe awọn eeyan kan ti iṣe Ọbalaye naa ko dun mọ ninu lo n lo ohun olohun tabi oju oloju lati fi ba kabiyesi lorukọ jẹ,

"Nigba ti a wo aworan ti arabinrin naa fi si ori itakun facebook rẹ, oju naa ko jọ eyi to wa si ayika kabiyesi tabi aafin ri."

Ọ̀ọ̀ni Ilẹ̀ Ifẹ̀ ní oun kò ṣ'àdéhùn ìfẹ́ pẹ̀lú Elizabeth Odunlami, tó ń gbé l'Amẹ́ríkà

Iroyin kan lọ kaakiri pe Ọọni ti ile ifẹ, Ọba Adeyẹye Ogunwusi ati omidan kan ti wọn pe orukọ rẹ ni Elizabeth Odunlami ẹni to ni ọrọ adehun ifẹ n bẹ laarin oun ati arole Oodua, Ọba Adeyẹye Ogunwusi ki kabiyesi tó to igba ifẹ rẹ pẹlu Yeyeluwa tuntun, Olori Naomi Shilẹkunọla laipẹ yii.

Amọṣa kabiyesi Ọọni ti ilẹ Ifẹ ti ṣalaye pe ko si ohun to jọọ eyi rara.

Àkọlé fọ́nrán ohùn,

Alaafin Ọyọ: Asiri agbara bibi ibeji lọpọ igba

Gẹgẹ bii ọrọ kan ti Oludari eto iroyin ati ipolongo ni Ile Oodua tii ṣe aafin Ọọni ti Ilẹ ifẹ, sọ 'awọn alagbeda ni wọn ti lu omidan naa ni jibiti pẹlu orukọ Kabiyesi' ati pe 'ẹsun ti ko lẹsẹ n lẹ ni eyi jẹ.'

Bi ẹ ko ba ni gbagbe laipẹ yii ni Kabiyesi Adeyẹye Ogunwusi bs si gbangba pẹlu Olori rẹ tuntun, Moronke Shilekunola lẹyin ipinya pẹlu olori ana, Zaynab Wuraọla.

O wa rọ awọn araalu, paapaa julọ awọn omidan lati kiyesara lori awọn ti n lo orukọ kabiyesi fi ja wọn lole ara.

Olori Zynab kí Yeyeluwa tuntun ti Ile ifẹ kú oríire

Olori Zynab

Oríṣun àwòrán, @oloriofficia

Àkọlé àwòrán,

Olóri Ìlé-Ifẹ tẹlẹ̀rí dáwọ ìdúnú pẹ̀lú Ọ̀ọ̀ni

Olorì Ile -Ifẹ tẹ́lẹ̀ri Zynab- Otiti Wuraola Obanor to jẹ́ olori láàfin tẹ́lẹ̀ri fun Ọba Adeyeye Ogunwusi tí gba ojú òpó instagram rẹ̀ lọ láti kí olori tuntun láàfin Kabiyesi, olori Shilekunola Monronke Oluwaseyi kú oríire.

Nínú ọ̀rọ̀ olori tẹ́lẹ̀ri, ó ni 'oore-ọ̀fẹ́ ń bẹ nínú ìdáriji, ẹwà sì ń bẹ nínú ìfọmọ̀niyan ṣe, mo kí Ọ̀ọ̀ni àti olori rẹ̀ tuntun'

Láìpẹ́ yìí ni kabiesi kéde ayàba láàfin fún ìgbà àkọkọ lẹ́yìn tí ìgbéyàwó òun àti Wuraola dàrú lọ́dun tó kọjá.

Shilekunola Naomi bọ̀wọ̀ fún àṣà ilẹ̀ Yorùbá kó tó wọlé tọ Ọọni

Àkọlé fídíò,

Olorí tuntun bọ̀wọ̀ fún àṣà ilẹ̀ Yorùbá

Ọọni ti Ile -Ife, Ọba Adeyẹye Ogunwusi, Ọjaja Keji ti kede arẹwa ọmọbinrin kan, Shilekunola Moronke Naomi gẹgẹbi olori laafin ni ọjọ kejidinlogun, oṣu Kẹwaa, ọdun 2018.

Ọba Ogunwusi fi eyi lede lori itakun ikansiraẹni Instagram rẹ wi pe isẹ Odumare ati awamaridi ni bi oun se fẹ olori naa, ti ọba si ki i kaabọ si aafin ọba.

Agbẹnusọ fun Ọọni, Moses Ọlafare sọ fun BBC Yoruba pe gbogbo awọn nkan to y ki olori tuntun ṣe lo ṣe ni ibamu pẹlu aṣa ilẹ Yoruba, ko to wọ iyẹwu kabiesi.

Wọ́n fa ayaba Naomi lé Ọ̀ọ̀nirìṣà lọ́wọ́

Oríṣun àwòrán, Il'e Oòduà

Àkọlé àwòrán,

Wọ́n fa ayaba Naomi lé Ọ̀ọ̀nirìṣà lọ́wọ́

Iyawo ọba tuntun naa, Shilekunola Naomi jẹ woli ati ajihinrere ni Ijọ En-Herald Ministries to ti jẹ adari ijọ naa.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Gẹ́gẹ́ bí àṣà Yorùbá, àti bí olùgbani nímọ̀ràn Ọba lórí ìròyìn ṣe sọ ọ́, gbogbo ètò tó yẹ sáàjú mímú olórì tuntun wọ ààfin ni wọ́n ti ṣe.

Wọ́n fa ayaba Naomi lé Ọọ̀ni'rìsà lọ́wọ́

Oríṣun àwòrán, Ile Oòduà.

Àkọlé àwòrán,

Wọ́n fa ayaba Naomi lé Ọọ̀ni'rìsà lọ́wọ́

Ọọni Ogunwusi ṣe ọjọ́ọ̀bí; Àwọn ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa rẹ̀ nìyí

Ọọ̀ni ilé Ifẹ̀, Ọba Adeyeye Ẹnitan Ogunwusi, Ọ̀jájá Kejì ń ṣe ayẹyẹ ọjọ́ ìbi ọdún Kẹrinlelogoji.

Àkọlé fídíò,

Ọọ̀ni ilé Ifẹ̀, Ọba Adeyeye Ẹnitan Ogunwusi, Ọ̀jájá Kejì ń ṣe ayẹyẹ ọjọ́ ìbi ọdúnKẹrinlelo

Tìlù-tìfọn sì ni wọ́n fi ṣe ayẹyẹ ọjọ́ ìbí ọ̀hún tó wáyé nílùú ilé Ifẹ̀.

BBC Yorùba bá Ọlọ́fà tì ìlú Ọ̀ffà, Ọba Muftau Gbadamosi, Esuwoye kejì sọ̀rọ̀ pe ko kí Ọọniriṣa kú ọdún, àṣèyí sẹ̀míì.

Ọlọ́fa dúpẹ lọ́wọ́ Ọ̀ọ̀ni Ifẹ̀ lori iṣẹ́ ribiribi tó ń ṣe láti ìgbà tó ti dé orí àpèrè àwọn baba rẹ̀. Ó ní gbogbo ọ̀nà tó ń gbà láti mú ìdàgbàsoké ba ilé yorùba jẹ ohun ìwúrí.

Àkọlé fọ́nrán ohùn,

Ọlọ́fà tí Ọffà:Mo kí Ọ̀ọ̀ni kú iṣẹ́ ribiribi fún ìdàgbàsókè ilẹ̀ Yorùbá

Ǹkan márùn-ún tó yẹ ko mọ̀ nípa Ọba Adeyeye Ogunwusi

Ó ṣe pàtàkì kí à sọ àwọn ǹkan tí ọ̀pọ̀ ènìyàn kò mọ nípa rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba yìí ṣe jẹ́ ọkan gbòógì nínú àwọn ọba aláde nílẹ̀ káàrọ̀-òòjíre.

Ọọni Ilé-Ifẹ̀ jẹ Atọbatẹlẹ, ko to jẹ Ọba, nitori ọmọ ọba ni. ldílé ọla Agbedegbede ní ilé oye Giesi ni wn ti bii, ó sì jẹ́ ọmọ Ọmọọba Aderopo àti Margaret Wuraola Ogunwusi.

Òsìṣẹ́ ní bàbá rẹ̀ nílé iṣẹ́ BCOS ati OSBC, kó tó fẹ̀yìn tì.

Akara Oyinbo
Àkọlé àwòrán,

Akara oyinbo ọjọ ibi Ọọni gbayi, o gba ẹ̀yẹ

Ọba Adeyeye pari ẹkọ́ rẹ̀ ní ilé ẹkọ́ gbogboniṣe Poly Ibadan (Ibadan Poly). Wọn si ti fi oye Ọmọwe da lọla ni fasiti NSUKA àti Egbinedon.

Asìkò tó wà ní ilé ẹkọ́ Poly Ibadan ló fún ọmọbirin kan, Omolara Olatubosun lóyún tó sì bí ọmọbinrin kan, Adeola Anuoluwapo Ogunwusi ẹni tó ti pé ọmọ ọdún mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n báyìí.

Ọ̀ọ̀ni ile ifẹ àti ọmọ rẹ̀ kan soso

Oríṣun àwòrán, Adesoye

Àkọlé àwòrán,

Ọ̀ọ̀ni ile ifẹ àti ọmọ rẹ̀ kan soso

Ọba Ogunwusi jẹ́ gbajúgbajà onísòwò nínú káràkátà ilé àti ilẹ̀, ó jẹ́ ẹlẹ́yinjú àànu tó maa ń fi owó soore fún àwọn tó ba kù díẹ̀ fún láwùjọ àti àwọn tó ba nílò ìrànlọ́wọ́.

O si maa n nawọ ìrànwọ́ nípaṣẹ̀ ilé alaanu Oduduwà Foundation àti Hopes Alive Initiative to da silẹ.

Awọn ẹgbọn Ọọni
Àkọlé àwòrán,

Ọmọ ìyá kìí yà, ọmọ baba ló n ba. Àwọn ẹ̀gbọ́n Ọ̀ọ̀ni nàá péjú síbi ayẹyẹ ọjọ́ ìbí rẹ̀

Ọjájá kejì máa ń jòkó gẹ́gẹ́ bíi adári ìgbìmọ̀ ilé ìfowópamọ Imperial Homes Mortgage, tó jẹ́ ẹka ilé ìfowópamọ Guarantee Trust Bank, bákan náà ló jẹ́ olùdarí Howard Roark Garden.

Shilekunola Naomi

Oríṣun àwòrán, Instagram/oonirisa

Àkọlé àwòrán,

Ọba Adeyẹye Ogunwusi, Ọjaja Keji ti kede iyawo tuntun laafin, lẹyin ti o se ayẹyẹ ọjọ ibi ọdun kẹrinlelogoji.

Ọọni ti Ile -Ife, Ọba Adeyẹye Ogunwusi, Ọjaja Keji ti kede arẹwa ọmọbinrin kan, Shilekunola Moronke Naomi gẹgẹbi olori laafin.

Ọba Ogunwusi fi eyi lede lori itakun ikansiraẹni Instagram rẹ wi pe isẹ Odumare ati awamaridi ni bi oun se fẹ olori naa, ti ọba si ki i kaabọ si aafin ọba.

Iyawo ọba tuntun naa, Shilekunola Naomi jẹ woli ati ajihinrere ni Ijọ En-Herald Ministries to ti jẹ adari ijọ naa.

Gẹ́gẹ́ bí àṣà Yorùbá, àti bí olùgbani nímọ̀ràn Ọba lórí ìròyìn ṣe sọ ọ́, gbogbo ètò tó yẹ sájájú mímú olórì tuntun wọ ààfin ni wọ́n ti ṣe.

Wọ́n fa ayaba Naomi lé Ọọ̀ni'rìsà lọ́wọ́

Oríṣun àwòrán, Ile Oòduà.

Àkọlé àwòrán,

Wọ́n fa ayaba Naomi lé Ọọ̀ni'rìsà lọ́wọ́

Ọọni Ogunwusi ṣe ọjọ́ọ̀bí; Àwọn ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa rẹ̀ nìyí

Ọọ̀ni ilé Ifẹ̀, Ọba Adeyeye Ẹnitan Ogunwusi, Ọ̀jájá Kejì ń ṣe ayẹyẹ ọjọ́ ìbi ọdún Kẹrinlelogoji.

Àkọlé fídíò,

Ọọ̀ni ilé Ifẹ̀, Ọba Adeyeye Ẹnitan Ogunwusi, Ọ̀jájá Kejì ń ṣe ayẹyẹ ọjọ́ ìbi ọdúnKẹrinlelo

Tìlù-tìfọn sì ni wọ́n fi ṣe ayẹyẹ ọjọ́ ìbí ọ̀hún tó wáyé nílùú ilé Ifẹ̀.

BBC Yorùba bá Ọlọ́fà tì ìlú Ọ̀ffà, Ọba Muftau Gbadamosi, Esuwoye kejì sọ̀rọ̀ pe ko kí Ọọniriṣa kú ọdún, àṣèyí sẹ̀míì.

Ọlọ́fa dúpẹ lọ́wọ́ Ọ̀ọ̀ni Ifẹ̀ lori iṣẹ́ ribiribi tó ń ṣe láti ìgbà tó ti dé orí àpèrè àwọn baba rẹ̀. Ó ní gbogbo ọ̀nà tó ń gbà láti mú ìdàgbàsoké ba ilé yorùba jẹ ohun ìwúrí.

Àkọlé fọ́nrán ohùn,

Ọlọ́fà tí Ọffà:Mo kí Ọ̀ọ̀ni kú iṣẹ́ ribiribi fún ìdàgbàsókè ilẹ̀ Yorùbá

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Ǹkan márùn-ún tó yẹ ko mọ̀ nípa Ọba Adeyeye Ogunwusi

Ó ṣe pàtàkì kí à sọ àwọn ǹkan tí ọ̀pọ̀ ènìyàn kò mọ nípa rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba yìí ṣe jẹ́ ọkan gbòógì nínú àwọn ọba aláde nílẹ̀ káàrọ̀-òòjíre.

Ọọni Ilé-Ifẹ̀ jẹ Atọbatẹlẹ, ko to jẹ Ọba, nitori ọmọ ọba ni. ldílé ọla Agbedegbede ní ilé oye Giesi ni wn ti bii, ó sì jẹ́ ọmọ Ọmọọba Aderopo àti Margaret Wuraola Ogunwusi.

Òsìṣẹ́ ní bàbá rẹ̀ nílé iṣẹ́ BCOS ati OSBC, kó tó fẹ̀yìn tì.

Akara Oyinbo
Àkọlé àwòrán,

Akara oyinbo ọjọ ibi Ọọni gbayi, o gba ẹ̀yẹ

Ọba Adeyeye pari ẹkọ́ rẹ̀ ní ilé ẹkọ́ gbogboniṣe Poly Ibadan (Ibadan Poly). Wọn si ti fi oye Ọmọwe da lọla ni fasiti NSUKA àti Egbinedon.

Asìkò tó wà ní ilé ẹkọ́ Poly Ibadan ló fún ọmọbirin kan, Omolara Olatubosun lóyún tó sì bí ọmọbinrin kan, Adeola Anuoluwapo Ogunwusi ẹni tó ti pé ọmọ ọdún mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n báyìí.

Ọ̀ọ̀ni ile ifẹ àti ọmọ rẹ̀ kan soso

Oríṣun àwòrán, Adesoye

Àkọlé àwòrán,

Ọ̀ọ̀ni ile ifẹ àti ọmọ rẹ̀ kan soso

Ọba Ogunwusi jẹ́ gbajúgbajà onísòwò nínú káràkátà ilé àti ilẹ̀, ó jẹ́ ẹlẹ́yinjú àànu tó maa ń fi owó soore fún àwọn tó ba kù díẹ̀ fún láwùjọ àti àwọn tó ba nílò ìrànlọ́wọ́.

O si maa n nawọ ìrànwọ́ nípaṣẹ̀ ilé alaanu Oduduwà Foundation àti Hopes Alive Initiative to da silẹ.

Awọn ẹgbọn Ọọni
Àkọlé àwòrán,

Ọmọ ìyá kìí yà, ọmọ baba ló n ba. Àwọn ẹ̀gbọ́n Ọ̀ọ̀ni nàá péjú síbi ayẹyẹ ọjọ́ ìbí rẹ̀

Ọjájá kejì máa ń jòkó gẹ́gẹ́ bíi adári ìgbìmọ̀ ilé ìfowópamọ Imperial Homes Mortgage, tó jẹ́ ẹka ilé ìfowópamọ Guarantee Trust Bank, bákan náà ló jẹ́ olùdarí Howard Roark Garden.