Koko iroyin: Winnie Mandela d'agbere f'aye, Ìkọlu Boko Haram ni Màìdúgùri

Eyi ni awọn akojọpọ iroyin ti toni.

Winnie Mandela di olóògbé lẹ́ni ọdún mọ́kànlélọ́gọ́rin

Oríṣun àwòrán, AFP

Àkọlé àwòrán,

Ibáṣepọ̀ Winnie àti ọkọ rẹ̀ dánmọ́rán bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ti kọ ara wọn sílẹ̀ ni 1996

Winnie Mandela, aya nígbà kan rí fún ààrẹ alawọ̀ dúdú àkọ́kọ́ ní orílẹ̀èdè South Africa ti papòdà lẹ́ni ọdún mọ́kànlélọ́gọ́rin.

Ìjáfáfá rẹ̀ farahàn lásìkò tí ó di òpó òṣèlú tí ọkọ rẹ̀ gbékalẹ̀ mú nígbà tí wọ́n jù ú sí ẹ̀wọ̀n gbére ní 1964.

Boko Haram pa èèyàn 25 ní Màìdúgùri

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Àkọlé àwòrán,

Boko haram tún ti s'oro ni Maiduguri

Àwọn ọmọ ikọ Boko haram tún ti s'oro ni Maiduguri, olú ìlú ìpínlẹ Borno, èyí tó ṣ'okùnfà ikú èèyàn mẹ́ẹ̀dógún tí àwọ̀n míràn tó dín díẹ̀ ni àádọ́rin sì farapa.

Ìròyìn fi ìdí rẹ múlẹ pé àwọn ọmọ ogun orílẹèdè Nàìjíríà pẹlú àwọn ọmọ ẹgbẹ adúnkùkùlajà Boko haram fìjà pẹẹta láwọn ìletò kan tí kò jìnà sí ìlú Maiduguri ni alẹ ọjọ àìkú. E ka ekunrere re ni bii

Awọn nkan miran ti ẹ ni lati mọ loni

Gbọ iroyin iṣẹju kan BBC

Fidio wa fun toni

Èkó: Àwọn akínkánjú obìnrín tó ń wa Márúwá

Àkọlé fídíò,

Èkó: Àwọn akínkánjú obìnrín tó ń wa Márúwá