Kókó ìròyìn t'òní: Ìdájọ́ ikú ní Èkìtì, Aláboyún f'ẹ̀hónú hàn l'Òǹdó

Eyi ni awọn akojọpọ iroyin ti toni.

Àwọn aláboyún f'ẹ̀hónú hàn lórí owó ìgbẹ̀bí ní ìpínlẹ̀ Òǹdó

Oríṣun àwòrán, Aproko Girl

Àkọlé àwòrán,

Awọn alaboyun f'ẹhonu han lori owo igbebi ni Akure

O kere tan, o to ọgọrun aboyun to rọ lọ si Ile-iwosan Alamọja ti ijọba ipinle Ondo nilu Akure ni Ojobo lati fẹhonu han lori awọn idiyele giga fun awọn itọju ati igbẹbi fun alaboyun ni ile iwosan naa.

Awọn obinrin aboyun, ti wọn ti ile-iwosan naa pa ṣe apejuwe awọn owo ti wọn n gba nile iwosan naa bi ohun ibanujẹ ati pe ojẹ ohun irẹjẹ fun ọpọlọpọ ninu wọn.

Ilé ẹjọ́ Èkìtì d'ájọ́ ikú f'ọ́kùnrin tó jí ọtí méje áti páálí sìgá

Oríṣun àwòrán, Erik S. Lesser/Getty

Àkọlé àwòrán,

Ìgò ọtí méje àti sìgá ṣokùnfà ẹjọ́ ikú

Ọkunrin kan ni ipinlẹ Ekiti, lorilẹede Naijiria ti ri idajọ iku he lẹyin to ji ọti ẹlẹrin dodo meje ati paali siga kan.

Ninu idajọ ti wọn gbe kalẹ ni ile ẹjọ giga to wa ni Ekiti, adajọ to pe orukọ ẹni ti wọn f'ẹsun kan naa gẹgẹ bii Babatunde jẹbi ẹsun ole jija ati nini ada ati okọ nigba ti wọn mu u wipe o jale. Ẹ ka ẹkunrẹrẹ rẹ ni bii.

Awọn nkan miran ti ẹ ni lati mọ loni

Gbọ iroyin iṣẹju kan BBC

Fidio wa fun toni

Màmá Boko Haram: Leah yóò padà sílé láì s'éwu

Àkọlé fídíò,

Boko Haram yóò dá Leah sílé