Kókó ìròyìn t'òní: Ìjọba Òǹdó lórí owó aboyún, Ìdigunjalé l’Ọ́ffà
Eyi ni awọn akojọpọ iroyin ti toni.
Ilé ìwòsàn Àkúrẹ́ ṣ'àlàyé lorí ìfowó kun owó ìbimọ
Oríṣun àwòrán, APROKO GIRL
Olùdarí ilé ìwòsàn ìjọbá Àkúrẹ́, dókítà Moses Adewọle, tí sàlàyé pe òwọn gógó ńǹkan lo faá ti wọn fi fi owó kun owó ìgb'ẹ̀bi.
Olùdarí ilé ìwòsàn náà sọ wipe ìwọdẹ́ ti àwọn aláboyún ṣe ni Ọjọ́bọ̀ (Thursday) ní àpẹrẹ òṣelù nínú.
Dókítà Adewọle sọ wipe wọn fi owó kun owó ìforukọ́ silẹ̀ fun àwọn alábọyún látí N2,500 si N4,000 ni nitori àti dí ònà owó ẹ̀yìn fún àwọn òṣìṣẹ.
Ọlọ́pàá Kwara ń wá àwọn adigunjalè tó pa èèyàn méjìlá
Oríṣun àwòrán, Ayobami Agboola
Ńse ni òkú èèyàn kún ilẹ̀ káàkiri ìlú Ọ̀ffà nítorí Ìsẹ̀lẹ̀ ìdigunjalè náà
Ile-isẹ ọlọpa lorilẹede Naijiria sọ wipe awọn n wa awọn adigunjale to yin ibọn pa ọlọpa mẹfa ati awọn ara ilu mẹfa nigba ti wọn ṣe ikọlu si ile ifowopamọ marun ni ilu Ọffa ni ipinlẹ Kwara to wa ni ẹkun iwọ oorun orilẹede Naijiria.
Awọn tọ rọ naa soju rẹ sọwipe awọn adigunjale naa ya bo agọ ọlọpa to wa ni agbegbe naa, ti wọn si pa awọn ọlọpa ati awọn to wa fẹjọ sun ni agọ ọlọpa, ko to di wipe wọn wa bẹrẹ si ni lọ si awọn ile ifowopamọsi lati lọ ja wọn ni ole. Ẹ ka ẹkunrẹrẹ rẹ ni bii
Awọn nkan miran ti ẹ ni lati mọ loni
Gbọ iroyin iṣẹju kan BBC
Fidio wa fun toni
Òkú sùn nínú ìṣẹ̀lẹ̀ ìdigunjalè ní Ọ̀ffà
Òkú sùn nínú ìṣẹ̀lẹ̀ ìdigunjalè ní Ọ̀ffà