Grace Olutọla: Lílo ọwọ́ òsì máa ń mú kí èèyàn tayọ láyé
Grace Olutọla: Lílo ọwọ́ òsì máa ń mú kí èèyàn tayọ láyé
Igbagbọ Yoruba ni pe lilo ọwọ osi jẹ ohun ẹgbin, iwa ibajẹ ati okunfa isẹlẹ buruku.
Amọ obinrin kan to n lo ọwọ osi, Grace Adunwọle Olutọla, lasiko to n ba BBC Yoruba sọrọ, tako iha Yooba yii si awọn eeyan to n lo ọwọ osi.
Adetọla ni, ko si iyatọ ninu kii eeyan lo ọwọ osi tabi ọtun, bẹẹ ni ko si ohun ti ọlọwọ ọtun n se, ti ọlọwọ osi ko lee se.
O tun kede pe ọwọ osi ni oun maa n fi tamba lẹyin igbọnsẹ, ti ọwọ osi lilo si maa n mu ki eeyan tayọ nile aye.
Bakan naa ni ọkọ rẹ, tun ti lẹyin pe, ọwọ osi ti iyawo oun n lo, lo mu ki oun nifẹ rẹ, to si jẹ ko rẹwa sii ni oju oun.
O fi kun pe lilo ọwọ osi maa n mu ki ọpọlọ ji pepe sii.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- ‘Èpè ni Toyin Abraham sẹ́ fún mi nínú ìgbìyánjú mi lórí ìgbeyàwó rẹ̀ tó dàrú’
- Ayélujára ló ń dá ìjà òsèré sílẹ̀ - Ọ̀gá Bello
- Alárùn ọpọlọ lu àwọn nọ́ọ̀sì àti dókítà agba níléèwòsàn ní àlùdákú
- Ikọ̀ ẹlẹ́sìn Hàkíkà rèé, níbití wọn ti ń pààrọ̀ ìyàwó láàrín ara wọn
- Ìwà olè ni kí pásítọ̀ máa bèèrè owó irúgbìn nínú ìjọ - Adelaja
- "Ohun tí ojú opó ń rí láwùjọ kò kéré"
- Ọsẹ́ tí òògùn Tramadol ń se nínú ara