Olusegun Obasanjo: Màá fi ìyókù ayé mi sin Ọlọ́run áti ènìyàn
Ààrẹ tẹ́lẹ̀ ní orílẹ̀èdè Nàíjíríà, Matthew Okikíola Arẹmu Olusegun Obasanjo, ti salaye pe koko ni ara ọta le fun oun, tori pe oun jẹ ọmọ oko.
Lásìkò tó ń bá BBC Yorùba sọ̀rọ̀, Ọbasanjọ ni ki ọ̀rọ̀ òun tó dayọ, ojú ti rí, pàápàá jùlọ lásìkò ti òun wà lọ́gbà ẹ̀wọ̀n.
Lasiko to n sọ ohun ti oju rẹ ti ri lọgba ẹwọn, Obasanjo sàlàyé pé, òhun kò ni ìrètí mọ ninu ọgba ẹwọn, nítori àṣẹ Abacha ni pé a fi ti òun ba kú ni òun àti àwọn méjì míràn to lé jáde lẹ́wọ̀n.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Lẹ́yìn ìfẹ̀yìntì ọdún márùn-ún, báágì àti bàtà ló kàn
- "Ìlú mímọ́ nibí, wọn kò gbọdọ̀ bímọ, sin òkú àbí ẹran síbẹ̀"
- Àràmọ̀ǹdà! Ọmọ ọdún mẹ́wàá ń fọn fèrè lágbo àríyá
- Baṣọ̀run Gáà, tó yan ọba mẹ́rin, pa ọba mẹ́rin àmọ́ ọba karùn-ún ló pa á
- Ìyá àgbà Ọlayinka, arúgbó tó ń ṣoge bí omidan
- Oshisko twins, àwọn 'ìbejì' tó ń dẹ́rìn ín p'òṣónú
- Wọ́n ta ère Ọ̀ṣun Osogbo sí Togo - Bàbá Ọṣun figbe ta
Ọbasanjọ ni riro ni ti eniyan lọrọ naa jẹ, tori sise ni ti Ọlọrun ọba, sùgbọ́n nípa ore ọfẹ́ Ọlọ́run, oun nìkan ni oun jáde laaye lọgba ẹwọn.
Obasanjo wá sàlàyé pé nígbà ti Ọlọ́run ti ṣe irú oore yìí fún oun, kò si ǹkankan to ku fun oun ju láti máa dúpẹ́ lọ.
Obasanjo dupe lọwọ Olorun pe oun pada jade lẹwọn.
O ni MKO Abiola, Oun ati Shehu Yaradua ni Abacha sọ pe awọn ko ni jade lẹwọn ṣugbon oun, Obasanjọ ri aanu gba.
O gbadura pe ki ohun rere pada jade lorilẹ-ede Naijiria laipẹ.