COZA RAPE Allegation: Ìdí rèé tí mi ò fi yọjú sí ìgbìmọ̀ àjọ PFN- Fatoyinbo

Oríṣun àwòrán, Instagram/BiodunFatoyinbo & BusolaDakolo
Oludasilẹ ijọ Commonwealth Of Zion Assembly ti ọpọ mọ si COZA, Biodun Fatoyinbo ti iyawo gbajugbaja olorin Timi Dakolo, Busola Dakolo fẹsun ifipabanilopọ kan ti ṣaleye pe agbẹjọro oun lo gba oun ni imọran pe k'oun maa yọju si igbimọ ajọ PFN.
Fatoyinbo sọrọ yii ninu atẹjade kan to fi sita lati ọwọ amugbalẹgbẹ rẹ, Ademola Adetuberu.
O sọ ninu atẹjade naa pe o ti gbangba pe igbimọ PFN yoo ṣegbe lẹyin ẹnikan ni ko jẹ ki oun lọ siwaju wọn.
- Ọwọ́ òfin ti tẹ ọ̀pọ̀ ọmọ Nàìjíríà lórí ẹ̀sùn jìbìtì l'Amẹrika- FBI
- Leon van Biljon dí èrò ọrun nípasẹ̀ Kìnìún rẹ̀
- Ikú dóró! Agbábọ́ọ̀lù Super Falcons tẹ́lẹ̀, Chiejine jáde láyé lẹ́ni ọdún 36
- PFN: Fatoyinbo kọ̀ láti yọjú ni ìwádìí wa kò ṣe parí
- Ilé iṣẹ́ márùn ún tí wọ́n dárukọ kìí ṣe túntun- Garba Shehu
- FRSC dá N443,180 padà fún ẹbí ẹni to ní ìjàmbá mọ́tò
- Ọlọ́pàá Germany ń wádìí àfurasí mẹ́rin nínú àwọn tó kọlu Ekweremadu ni Germany
- Iṣẹ́ bọ́ lọ́wọ́ ọlọpàá mẹ́rìn to pa afurasí, wọ́n tún dèrò ẹ̀wọ̀n
Adetuberu ṣalaye ninu atẹjade ọhun pe lootọ ni pasitọ Akinola Akinwale pe Fatoyinbo lori aago pe ko wa farahan niwaju igbimọ PFN, ṣugbọn COZA sọ fun un pe ko le wa nitori iwadii si n lọ lọwọ lori ẹsun ti Busola fi kan an.
O fikun ọrọ pe agbẹjọro sọ fun Fatoyinbo wi pe ko maa yọju si igbimọ naa nitori aarẹ ajọ PFN, Bisọpu Felix Omobude ti sọ tẹlẹ pe oun o mọ Fatoyinbo ri.
Adetuberu tun sọ pe niṣe ni igbimọ ajọ PFN tun kọ lati fi iwe pe Fatoyinbo.
O ni Fatoyinbo yoo yọju si igbimọ PFN tawọn ọlọpaa ba pari iṣẹ iwadii wọn lori ọrọ naa.
PFN: Fatoyinbo kọ̀ láti yọjú ni ìwádìí wa kò ṣe parí
Ajo awọn ẹni ẹmi ni Naijiria, eyi ti wọn n pé ni Pentecostal Fellowship of Nigeria (PFN), ti fi ọrọ lede pe awọn ko tii pari iwadii ti wọn n ṣe lori ẹsun ifipabanilopọ ti Busọla Dakolo fi kan Biọdun Fatoyinbo.
Ẹni ti o jẹ akọwe fun ẹgbẹ naa, Biṣọọbu Emma Isong lo fi ọrọ naa lede nigba ti o n ba ileeṣẹ BBC sọrọ nilu Eko lowurọ oni.
O sọ ninu ifọrọweró naa pe: olusọ agutan Biodun Fatoyinbo kọ lati yọju si ibi iwadii ti ajọ naa gbe kalẹ, bi o tilẹ jẹ pe, Busọla Dakolo ti yọju nitirẹ.
Oríṣun àwòrán, Biodun Fatoyinbo/Facebook
Fatoyinbo kọ̀ láti yọjú ni ìwáàdí ò ṣe parí
Awọn ajọ tó ń rí sí ọ̀rọ̀ ilé ìjọsìn pẹntikọsita ní Nàìjíríà (PFN) ti so pe iwadi ajọ naa si ẹsun ifipabanilopọ ti Busola Dakolo fi kan oludasilẹ ijọ Commonwealth of Zion Assembly (COZA), Pasitọ Biodun Fatoyinbo ko pari.
Oríṣun àwòrán, Busola Dakolo/Facebook
Ìwáàdí ẹ̀sùn ìfipábánilòpọ̀ kò tíì parí
Ajọ PFN sọ pe iwadii naa ko pari nitori Pasitọ Fatoyinbo kọ lati yọju si igbimọ ẹlẹni marun-un to n ṣewadii ẹsun naa.
O te siwaju ninu ọrọ pe "iwadii ti ẹgbẹ PFN ṣe ko nii ṣe pelu iwadii ti awọn ọlọpaa."
COZA: Ọpọ èrò ló jáde ṣe lòdì sí ẹ̀sùn ìfipábánilòpọ̀ Fatoyinbo
Iwadii ẹgbe PFN lo waye nitori awuyewuye awọn eniyan ati awọn oniroyin lori ẹsun naa.
Oríṣun àwòrán, @others
A gbọ ẹjọ ẹnikan da...