Kolawọle Ajeyẹmi: Ó yẹ ká ro ọjọ́ ìkúnlẹ̀ bímọ mọ́ aya lára lásìkò tó bá ṣẹ̀ wá

Obiri ti wọn n pe ni obinrin! Kolawole Ajeyemi, to ṣẹṣẹ bi ọmọ tuntun jojolo pẹlu gbajugbaja oṣere tiata, Toyin Abraham, ti ṣapejuuwe awọn obinrin gẹgẹ bi ohun eelo ẹlẹgẹ lawujọ.
Ṣugbọn o ni bi wọn ṣe jẹ ohun ẹlẹgẹ, naa ni wọn ṣe lagbara to, pẹlu afikun pe ti Eleduwa ba fi obinrin rere jinki ọkunrin kan, iru ọkunrin bẹẹ ti ri ibukun, idunnu ati ẹmi gigun gba lọdọ Ọlọrun.
- Toyin Abraham kìí bá èmi náà yọ̀, ni kò jẹ́ kí ń gbé e lárugẹ fún ayọ̀ ọmọ - Lizzy Anjorin
- Iṣẹ́ ọpọlọ ló yẹ ká ṣe nínú tíátà, kìí ṣe àfihàn ara bíbó àbí ìhòòhò wa - Binta Mọgaji
- Èmi àti Saheed kìí ṣe ọmọdé, a ti jọ ṣe Sinimá papọ̀, èyí túmọ̀ sí pé ìjà ti parí - Fathia Balogun
- Ọ̀pọ̀ èèyàn bẹnu ẹ̀tẹ́ lu Mercy Aigbe lórí bó ṣe ki Adeniyi Johnson
- Àjẹ́ àti Aṣẹ́wó ní ìyá Rainbow - Òjòpagogo
- N30,000 ni mo gbà fún orí, ọwọ́ àti ẹran ara wòlíì Bosede - Kayeefi
O ni wiwa pẹlu aya oun, Toyin lasiko to wa nile igbẹbi, to si n rọbi lọwọ, ti jẹ ki oun mọ ohun to maa n jẹ ki awọn ọkunrin kan maa n kẹ iyawo wọn gẹgẹ, toju-timu.
Ọkọ Toyin, ẹni to sọrọ naa loju opo Instagram rẹ, @kolawoleajeyemi ni ṣe irora, omije ati ọpọ nkan miran ti ko see sọ, ti aya oun la kọja nigba to fẹ bi ọmọ ti Ọlọrun fi tawọn lọrẹ ni k'oun sọ ni, o ni ẹnu oun ko le sọọ tan.
Ajeyẹmi ohun toju awọn obinrin n ri nigba ibimọ ti to kawọn ọkọ wọn maa dariji wọn nigba ti wọn ba ṣẹ wọn.
O wa rọ awọn ọkunrin wi pe ki wọn gbiyanju lati tọju iyawo wọn nitori awọn lo jẹ iya ati iyawo fun wọn.
Amọ ko sai yan pe, arọwa oun fawọn ọkunrin lati maa tẹ jẹjẹ pẹlu awọn aya wọn ko tumọ si pe, oun n fun awọn obinrin lasẹ lati maa siwahu, sugbọn ohun ti oun n sọ ni pe awọn obinrin nilo ikẹ ọkunrin.
O ni " Ẹ́ jẹ ka maa tọju, ka si maa sikẹ awọn obinrin nitori awọn ni iya ati iyawo wa, ko si ohun meji to tọ si wọn ju ojurere wa lọ, mo si bọwọ fun awọn obinrin rere."
- Ìdẹ̀ra dé, Gẹnẹrátọ̀ tó ń lo omi dé, a bọ́ lọ́wọ́ òkùnkùn
- Ìkúnlẹ̀ àbiyamọ o! Saudi fẹ́ gbẹ̀mí 23 ọmọ Nàìjíríà tó gbé òògùn olóró
- Ìjọba, ẹ yé fi ọlọ́pàá àtàwọn ológun dúnkokò máwọn èèyàn- Ṣoyinka
- Irọ́ ló pa, a kò mọ̀ ọ́ rí tàbí fún ọ ní ₦13m - APC tako afurasí ajínigbé
Ajeyẹmi wa gbadura fun gbogbo awọn obinrin rere fun ibukun Ọlọrun lori wọn, bakan naa lo gbadura pe wọn o jere iṣẹ ọwọ wọn.