Ghana Floods: Omiyalé ní Ghana, èèyàn 28 dolóògbé!
O kere tan eniyan mejilelogun lo ti doloogbe ni orilẹ-ede Ghana bayii.
Lataari arọọrọda ojo to n rọ lati ọjọ mẹjọ sẹyin lo ti fa omiyale ati agbara ya ṣọọbu ni ariwa ila oorun Ghana.
O le lẹgbẹrun kan ile to ti da wo silẹ ti ọpọ eeyan ko si nile lori mọ ni ẹkun yii
Ẹru n ba awọn alaṣẹ Ghana pe ki oku ma lọ pọ sii ju bayii lọ, ti awọn ti wọn ko nile lori naa si n pọ sii.
- Bóò bá ní nọ́mbà ìdánimọ̀ NIN, à tí kọ ìdánwò rẹ yóò ṣòro
- BBC 100 Women 2019: ọ̀pọ̀ obìnrin ilẹ̀ Afirika ń gbàràdá!
- Mo mọ̀ pé àwọn aṣòfin máa ṣatìlẹyìn tó yẹ fún mi- Boris
- Iṣẹ́ ti bẹ̀rẹ̀ lórí àfikún owó oṣù tuntun- Keyamo
Ajọ to n mojuto iṣẹlẹ pajawiri ni Ghana, National Disaster Management Organisation ti berẹ si ni pin awọn ohun eelo fawọn ti omiyale le kuro nile.
George Ayisi to jẹ alukoro ajọ naa ṣalaye pe, oku eniyan mejilelogun ni wọn ti ri bayii ni eyi ti awọn ogoje eeyan dẹ ti di alainile lori.
- World Food Day: Wo àwọn oúnjẹ ìṣẹ̀mbáyé Yorùbá tó ti ń di àpatì
- Kí ló ń fa ìjàmbá omíyale ní Naijiria?
- Omíyalé àgbàrà ti ya ṣọ́ọ̀bù ní Niger
- Ìjọba Ondo kéde ìsimi ọ́sẹ̀ mẹ́ta fún àwọn ilé ìwé to lùgbàdì omíyalé!
Pupọ ninu awọn ti ile wọn ti wo ni wọn ti ko lọ sile ijọsin lawọn ṣọọṣi wọn ati awọn ile iwe kọọkan.

Ajọ to n woye ayipada oju ọjọ ni orilẹ-ede Ghana ti sọ pe ọpọ ojo lo ṣi maa rọ sii lọdun yii ni Ghana.
Osu kẹrin, ọdun yii niru omiyale bayii ṣẹle gbeyin ni Ghana.

Akẹ́kọ̀ọ́ Ilaro Poly tó pegedé jù jẹ ẹ̀bùn iṣẹ́ ọ̀fẹ́ lọ́wọ́ Gómìnà Abiodun
Ẹ gbà mi o! Wọ́n tún ń lépaà mi o! - Kemi Afolabi
Njẹ́ o mọ pé N3000 ló o sàn láti gbà kaadi ìdánimọ̀ míì bí tí tẹ́lẹ̀ bá sọnù?
BBC 100 Women 2019: Wo ọmọ Nàíjíríà kan tó wà nínú wọn
