Amotekun Recruitment: Ìròyìn ayọ̀ fún gbogbo àwọn tó forúkọ sílẹ̀ fún ikọ̀ Amotekun ní ìpínlẹ̀ Oyo

Ijọba ipinlẹ Oyo ti kede pe orukọ awọn to yege lati darapọ mọ ikọ alabo Amọtekun ti jade.
Ninu atẹjade ti adari ikọ naa ni ipinlẹ Oyo, Ajibola Kunle Togun, fi lede, o ni gbogbo awọn to forukọ silẹ si oju opo ti ijọba gbe kalẹ fun ikọ naa lati lọ wo orukọ wọn.
O ni "ki gbogbo awọn to yege ninu iforukọsilẹ ọhun lọ si ile ẹkọṣẹ awọn olukọ, Emmanuel Alayande, to wa ni ilu Oyo laago mẹsan owurọ lọjọ kẹta, oṣu Kọkanla, ọdun 2020, fun eto iforukọsilẹ ni kikun."
- Alága ìjọba ìbílẹ̀ Iganna, Jacod Adeleke ti gba òmìnira lọ́wọ́ àwọn ajínígbé - Ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Oyo
- Ọlọ́pàááá! Ẹ padà sẹ́nu iṣẹ́ kíá bí bẹ́ẹ̀ kọ́... Àmọ́ ẹ ríi pé ẹ dáàbò bo ẹ̀mí yín - Ọ̀gá àgbà ọlọ́pàá
- Wumi Toriọla ti sọ̀rọ̀ sóke láti fi idí rẹ̀ múlẹ̀ pé òun àti ọ̀rẹ́ òun níjà
- Ojúmọ́ kan, ìdàmú kan ni mo fi lo ogún ọdún àkọ́kọ́ lórí oyè - Alaafin
O fi kun pe igbaradi ati idanilẹkọọ fun awọn eeyan na yoo waye fun ọsẹ meji gbako.
Oríṣun àwòrán, Western Nigeria security network
Atẹjade ọhun tẹsiwaju pe ki awọn eeyan naa mu ṣokoto pelebe alawọ buluu, aṣọ funfun ati bata kanfasi to ṣee sare lọwọ.
Tóo bá pá lórí, Mílíìkì sóyà àtàwọn ǹkan mẹ́ta yìí leè mú irun rẹ hù padà!
Ko tan sibẹ, o tun ni ki wọn ko ike iwe, ago imumi, ṣibi, abọ ounjẹ ati igbalẹ lọwọ.
Adari ikọ naa pari ọrọ rẹ pe ki awọn ti orukọ wọn ko jade má ṣe iyọnu lati yọju si ọgba ileewe ti idanilẹkọọ ati igabradi naa yoo ti waye.
- Tí iye iná tí ẹ rí gbà bá kéré ju owó tí ẹ rà á lọ, ẹ ti jẹ gbèsè tẹ́lẹ̀ ni - Iléeṣẹ́ apínnáká
- Ẹ gbọ́ Ohun tí Desmond Elliot àti Mojisola Alli-Macaulay sọ lórí ayélujára táwọn ọmọ Nàìjíríà fi ìbínú
- Mo pinu láti dá Iphone tì mo mú padà kí ọlọ́pàá tó mú mi
- Àwọn olóṣèlú Nàìjíríà márùn ùn tó sọ̀rọ̀ tí ará ìlú fà ìbínú yọ
Gómìnà Seyi Makinde fẹ́ kó bọ́ọ̀sì elérò ọgọ́rùn-ún bóòde láti máa ná Ibadan sí ìpínlẹ̀ míì
Oríṣun àwòrán, Seyi Makinde
Ijọba ipinlẹ Oyọ ti ni awọn yoo lo ọkọ tuntun to le lọgọrun naa lati fi maa na gbogbo awọn ipinlẹ to wọ ipinlẹ Oyo.
Kọmisọna fun eto iroyin, Wasiu Olatunbosun lo sọ bẹẹ fun BBC Yoruba lẹyin ti ijọba kede wi pe awọn fẹ ra ọkọ tuntun yii fun idagbasoke eto irinna ni ipinlẹ naa.
Olatunbosun ni ijọba fẹ lo iye owo to to N9.3 billiọnu lati fi ra awọn ọkọ nla fun irinna ọkọ laarin ipinlẹ naa.
Ọkọ kọọkan yoo ma a gbe to eniyan ọgọrun, ti yoo si ma a lọ si Ogbomoso, Oyo, Ibarapa ati bẹẹ bẹẹ lọ''.
- Àwàdà tàbí óótọ́, kì lò f'ẹkún Kọmíṣọ́nnà ìlera Kogi lórí amóhùnmáwòrán?
- Ẹ gbọ́ ohun tí Desmond Elliot sọ lórí ayélujára tó bí àwọn ọmọ Nàìjíríà nínú
- Ṣé o mọ̀ pé o leè forúkọ̀ iléeṣẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ lọ́fẹ̀ẹ́? Oníṣẹ́ àdáni 250,000 ni ìjọba ṣe ìlànà yìí fún
- Ẹ má gbìyànjú láti bo àṣírí ìpànìyàn tó wáyé ní Lekki, á ní ẹ̀rí tó dájú - Amnesty International
- Àkùkọ dojú ìjà kọ ọlọ́pàá, ikú ló já sí fún agbófinró
Kété tí wọ́n bá ti báa yín sùn tàn torí pé ẹ tóbi, ẹ gbà pé ìfẹ́ yẹn ti parí - Auntie Remi Ọlọ́yàn ńlá
''Ọkọ naa wa lati fi pa owo si apo ijọba ni nitori awọn ọkọ to wa nilẹ ti n bajẹ, eleyii to n fa inira fun awọn eniyan wa.''
''Ti wọn ba n wọ moto naa, inira yoo dinku fun irinkerindo fun awọn eniyan naa''
''Kii ṣe ọfẹ ni o ma ba de, owo ti awọn eniyan ba n san gẹgẹ bi owo ọkọ ni a ma a fi san owo naa pada.''
'' Wọn a fun awọn oṣiṣẹ ijọba ni ọkọ ẹyọkan lati ma a wọ lọfẹ lati ibi iṣẹ ati awọn ọmọ ileewe ni ọfẹ lati ma a fi rin lati ibi kan si omiran.''
Ijọba ipinlẹ Oyo fikun wi pe awọn ọkọ naa yoo mu igbeyagbadun ba awọn eniyan, ti ilọsiwaju yoo fi ba wọn.
'Egbò tó ti fẹ́ẹ̀ jiná ni ìtàn bí wọ́n ṣe pa Soun Ogbomoso, Ọba Olayode tẹ ń bèrè'
Wákàtí méjì àbọ̀ ní àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tó wọlé iléèwè padà yóò fi kẹ́kọ̀ọ́ lójúmọ́ - Ìjọba Oyo
Nipinlẹ Oyo, wakati meji aabọ ni akẹkọọ yoo fi wa nileewe lojumọ
Bi ojumọ se n mọ, ni ofin ati ara tuntun n jade lẹka eto ẹkọ nilẹ wa, eyi to lee mu agbega abi akude ba ilana eto ẹkọ ilẹ wa.
Ni asiko ti ajakalẹ arun Coronavirus wọle de, oniruuru ilana eto ẹkọ nijọba ti gbe sita, eyi to wa lati daabo bo awọn akẹkọọ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Kí ló wà láàrin Olorì Badra àti Bobrisky, tí ọ̀rọ̀ wọn fi wọ̀?
- Bí pínpín owó ilù ṣe díjà sílẹ̀ láàrin àwa ìjòyè àti Oluwo rèé - Osa Iwo
- Kí ló mú kí ọkọ̀ kan tó jóná ráùráú lórí afárá Ojuelegba?
- Wo ẹ̀bùn àti owó tí àwọn olùkópa ti jẹ lórí ètò BBNaija season 5
- Kíni 'Ẹ̀lẹ̀ daddy' Olorì Abbey Adeyemi ṣe tí ojú òpó ayélujára Instagram rẹ̀ fi ń yeruku lálá?
- Ìkébé mi tóbí ju ohun tí mo lè dọwọ́ bò lọ, n kìí fí ṣakọ- Nkechi Blessing
- Ẹ̀yin òṣìṣẹ́, ẹ má ṣáì lọ síbi iṣẹ́ lọ́jọ́ Ajé, olórí àwọn òṣìṣẹ́ ní Nàìjíríà tako ìyanṣẹ́lódì
Nipinlẹ Ọyọ ẹwẹ, ijọba tun ti fi ilana miran sita lori ilana eto ẹkọ fawọn akẹkọọ to sẹsẹ pada sile ẹkọ lọjọ Aje to kọja.
Bẹẹ ba si gbagbe, yoo to osu mẹfa tawọn ileewe fi wa ni titipa nitori arun Coronavirus, tawọn akẹkọọ si fidi mọle wọn.
Amọ atẹjade miran tileesẹ eto ẹkọ nipinlẹ Ọyọ fisita lọjọ Ẹti, ọjọ kẹẹdọgbọn osu Kẹsan ọdun yii fihan pe atunse tun ti ba eto ẹkọ lawọn ile ẹkọ tijọba ati taladani to wa nipinlẹ naa.
Atẹjade naa ti Kọmisana feto ẹkọ nipinlẹ Ọyọ, Olasunkanmi Olaleye fọwọsi sisọ loju rẹ pe, wakati meji ati aabọ pere lawọn akẹkọọ yoo maa fi kawe bayii, ti wọn si pin wọn si isọri meji.
Oríṣun àwòrán, Oyo state ministry of education
Isọri alakọkọ ni yoo wọle sile ẹkọ lati aago mejọ aarọ si aago mẹwa abọ aarọ, ti wọn yoo si pada sile wọn.
Isọri keji awọn akẹkọọ naa ni yoo bẹrẹ ikẹkọọ ni aago mẹwa abọ aarọ, ti wọn yoo si pari ni aago kan ọsan.
Isọri kọọkan awọn akẹkọọ ọhun ni yoo wa nile ẹkọ fun wakati meji aabọ pere.
Ijọba ni awọn gbe igbesẹ ọhun lẹyin toun ti fikunlukun pẹlu awọn eeyan ati ẹka ti eto ẹkọ gberu.
Pupọ awọn obi lo pese awọn ibomu fawọn ọmọ to pada si ileewe.Ijọba ko pese rẹ fun wọn
Kọmisana feto ẹkọ salaye pe, isẹju mẹẹdọgbọn pere ni wọn yoo fi maa se idanilẹkọọ fawọn akẹkọọ lori isẹ kọọkan, ti wọn yoo si se isẹ mẹfa laarin wakati meji aabọ lojumọ.
Amọ to ba di ọjọ Ẹti, isẹ marun ni wọn yoo maa se lojumọ, ti wọn si rọ awọn ọga lati tẹle ofin naa.
Akẹ́kọ̀ọ́ wọlé padà, ìjọba Oyo kò pèsè ìbòmú lòdì sí ìlérí rẹ̀
Ni ibamu pẹlu aṣẹ ti ijọba pa fun gbogbo ile ẹkọ to n bẹ n'ipinlẹ Ọyọ, awọn akẹkọọ to n bẹ ni kilaasi ikẹfa nile ẹkọ alakọbẹrẹ, kilaasi ikẹta ati ikẹfa nile ẹkọ girama, ti wọle pada sẹnu ẹkọ lonii.
Gbogbo ile ẹkọ ti ikọ BBC Yoruba ṣe abẹwo si, lo ṣe amulo awọn ohun elo ti o le daabo bo akẹkọọ ati olukọ lọwọ kokoro Coronavirus, bẹrẹ lati orii omi ati ọṣẹ, iboju, to fi mọ ilana itakete si ara ẹni.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Kàkà k‘éwé àgbọn dẹ̀ lágbo òṣèlú l‘Ondo, akọ̀wé ìjọba tún kọ̀wé fipò sílẹ̀
- Ẹ wo bí ọ̀rọ̀ òṣèlú, ẹ̀sìn àti ẹ̀yà ṣe fa ogun abẹ́lé Biafra
- Mà á gbẹ̀san bàálù àjọ UN tó já ní Borno - Buhari yarí
- Ẹ̀kún omi ṣọṣẹ́ ní Ogun, ìjọba yarí láti wó ilé ojú odò
- Ẹ sá àwọn akẹ́kọ̀ọ́ sínú òòrùn fún ọgbọ̀n ìṣẹ́jú lójojúmọ́ - Ìjọba Oyo pàṣẹ
- Òṣìṣẹ́ LASTMA gún olólùfẹ́ rẹ̀ l'ọ́bẹ, ó tún gba ẹ̀mí ara rẹ̀ l'Eko
Lara awọn adari ile ẹkọ to ba wa sọrọ ṣe alaye wi pe, gbogbo ipa ni awọn n sa lati daabo bo awọn akẹkọọ ati awọn olukọ wọn gẹgẹ bi wọn ṣe wọle pada sẹnu ẹkọ.
Wọn ni akẹkọọ tabi olukọ ti ko ba lo ibomu ko ni lanfani lati wọle si inu ọgba ile ẹkọ.
Ọpọlọpọ akẹkọọ ti ko lo ibomu si ni wọn da pada sile lẹnu iloro lasiko ti ikọ BBC Yoruba ṣe abẹwo si awọn ile ẹkọ kan niluu Ibadan lọwurọ ọjọ Aje.
Awọn adari ile ẹkọ naa tẹsiwaju wi pe, ijọba ipinlẹ Ọyọ tun ti paa laṣẹ fun wọn lati maa ko awọn akẹkọọ naa si ita gbangba, fun bii ọgbọn iṣẹju.
Laarin aago mọkanla si mọkanla aabọ lojoojumọ si ni eto naa yoo maa waye, ninu igbiyanju lati mu adinku ba itankalẹ aarun aifojuri, ‘Coronavirus’.
Lori ipese awọn ohun elo idaabo bo ara ẹni bii ibomu, iboju ati ogun apakokoro, awọn aṣoju ile ẹkọ naa sọ fun akọroyin wa wi pe, lati ọwọ ara wọn ni wọn ti pese awọn ohun elo naa.
Eyi si tako ileri ti ijọba ṣe lati pese ohun elo idaabo bo ara ẹni fun awọn akẹkọọ.
Awọn aye to ṣi silẹ ni kilaasi awọn akẹkọọ ti ijọba ko tii fun ni aye lati wọle pada, lo mu ki itakete si ara ẹni di irọrun fun awọn akẹkọọ to wọle pada lonii.
Ọpọlọpọ kilaasi gan an ni awọn akẹkọọ to n bẹ ninu rẹ ko to ogun, pẹlu bi o ṣe jẹ wi pe, aye akẹkọọ bii ọgbọn ni ijọba ipinlẹ Ọyọ sọ wi pe ki wọn pese silẹ.
Ẹ sá àwọn akẹ́kọ̀ọ́ sínú òòrùn fún ọgbọ̀n ìṣẹ́jú lójojúmọ́ - Ìjọba Oyo pàṣẹ
Oríṣun àwòrán, @OfficialSeyiMakinde
Ijọba ipinlẹ Ọyọ ti pasẹ fun awọn ọga agba ileẹkọ gurama ati ti alakọbẹrẹ jakejado ipinlẹ naa lati sa awọn akẹkọọ wọn sinu oorun fun ọgbọn isẹju lojooju.
Kọmisana feto ẹkọ, Olasunkanmu Aremu Olaleye lo sisọ loju ọrọ yii ninu atẹjade kan to fi ransẹ si awọn ọga ile ẹkọ naa ati awọn eeyan miran ti ọrọ eto ẹkọ gberu.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ikọ̀ ìjọba Ọ̀yọ́ dé lásìkò tí kò yẹ ni wọn kò ṣe wọlé - Ẹ̀bí Ajimobi fèsì
- Ọ̀pọ̀ èèyàn tí kò yin Ajimobi lojú ayé, tó ń yìn-ín lẹ́yìn ikú, yóò jẹ ìyà - Oníwáàsí
- Ọ̀pọ̀ ìgbà ní Hushpuppi àtàwọn èèkàn PDP ti ya fọ́tò ní Dubai, EFCC ẹ wádìí wọn - APC ń lọgun
- Àwòrán rèé nípa àwọn gbajúmọ̀ tó ti bá Hushpuppi ṣe
- Mo ti bá ọmọ ọwọ́ mẹ́ta lòpọ̀ sẹ́yìn, ọmọ oṣù mẹ́ta ló ṣìkẹrin - Afurasí jẹ́wọ́
Atẹjade naa, to bọ sita ni ọjọ Keji osu Keje ọdun 2020 tun kede pe, kikida awọn ile ẹkọ tijọba fi ọwọsi, to si ni iwe ẹri pe o peju sibi idanilẹkọ nipa arun Coronavirus nikan ni yoo jẹ sisi lonii.
Lẹ́yìn ò rẹyìn, ilé ìwé di ṣíṣí padà ní ìpínlẹ̀ Oyo
Oríṣun àwòrán, @OfficialSeyiMakinde
Awọn alaṣe ni ẹka eto ẹkọ ni ipinlẹ Oyo ti gbaradi fun aṣẹ ijọba lati jẹ ki awọn akẹkọọ pada si ileewe, lẹyin ti wọn ti ileewe nitori arun Coronavirus.
Kọmisọna fun eto ẹkọ, imọ sayẹnsi ati iṣẹ ẹrọ, Olasunkanmi Olaleye ni awọn akẹkọọ ni ileewe Alakọbẹrẹ ati Girama ti wọn ti fẹ kẹkọ jade, yoo bẹrẹ ileewe pada ni oni, Ọjọ Aje, Ọjọ Kẹfa, Oṣu Keje, ọdun 2020.
Olaleye ni ijọba ti gbe eto kalẹ lati ri pe awọn akẹkọọ wa ni alaafia lasiko arun Coronavirus yii.
Oludasilẹ ile ẹkọ adani kan naa fidi rẹ mulẹ pe, awọn ọga agba ileewe ni ipinlẹ Oyo, ti ṣe ipade lori eto ti wọn gbọdọ ti ṣe kalẹ fun awọn akẹkọọ, ki arun Coronavirus ma ba tan kalẹ si laarin awọn akẹkọọ.
Mama Arsenal: Màmá àgbà yìí máa ń lọ sí ìbùdó tí wọ́n ti ń wo bọ́ọ́lù láti wòran
"O pọn dandan ki awọn akẹkọọ to ba n bọ ni ileewe lo ohun elo ibomu, nigba ti awọn alaṣẹ ileewe yoo ri pe awọn akẹkọọ tẹle ofin ijinasiraẹni, ipese omi lati fọ ọwọ wọn lore-koore, ipese ẹrọ ti wọn fi n mọ bi ara ṣe gbona si, ati bẹẹ bẹẹ lọ.
Awọn obi kan naa ni iwọle pada awọn akẹkọọ yoo dara, ti wọn ba tẹle ofin ti ijọba lakalẹ lati dẹkun itankalẹ arun Coronavirus.
Oríṣun àwòrán, @OfficialSeyiMakinde
Bakan naa ni awọn akẹkọjade ni inu awọn dun lati pada si ileewe, bẹẹ si ni awọn akẹẹgbẹ awọn fi idunnu wọn han si pipada si ẹnu ẹkọ wọn.
Lẹ́yìn ọdún mẹ́jọ̀, ìjọba Ọyọ bẹ̀rẹ̀ owó ẹ̀náwò àtìgbàdégbà padà fún àkóso ílé ẹ̀kọ́
Gomina ipinlẹ Oyọ Onimọ ẹrọ Ṣeyi Makinde ti fọwọ si sisan owo to to okoolelẹẹdẹgbẹta ati mẹfa miliọnu naira (₦526) fun gbogbo ile iwe ijọba gẹgẹ bi owo ẹnawo atigbadegba fawọn ileewe ijọba bii ẹgbẹrun meji aabọ.
Atẹjade kan tijọba fisita lo sisọ loju ọrọ yii pẹlu afikun pe wọn ti fi owo to to irinwo miliọnu naira (₦400m) ṣọwọ si awọn ile iwe girama, nigba ti ile iwe alakọbẹrẹ naa si ti tẹwọ gba aadoje miliọnu naira o din mẹrin ( ₦126m) bakan naa.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Omi ìṣẹ̀ńbáyé tó ń dà ní Ówù rèé, èyí tó ga jùlọ ní Afirika
- Mo kan wàhálà lálẹ ọjọ ìgbeyàwó torí ìbálé mi kò ṣe ẹjẹ - Ìyàwó ọ̀sìngín
- Akẹ́kọ̀ọ́ tó gbèlé kàwé pegede wọ fásítì lọ́mọ ọdún méjìlá
- Ẹgbẹ́ òṣèlú AA kò gbọdọ̀ kópa nínú ìdìbò gómìnà ní Kogi, Bayelsa - Ilé ẹjọ́
- Ẹ̀kun omi wo ògiri ọgbà ẹ̀wọ̀n, ẹlẹ́wọ̀n 150 sálọ
Owo yii ni Ijọba lo wa fun ẹnawo atigbadegba awọ̀n ileewe naa fun taamu akọkọ ninu saa eto ẹkọ ọdun 2019 si 2020, ti wọ̀n si ti pasẹ fawọn ọga agba ileẹkọ alakọbẹrẹ ati girama naa lati lọ si apo asuwọn owo ni banki ki wọn lee gba owo naa ni kiakia.
Ojilelẹgbẹta ile iwe girama lo wa yika ipinlẹ Ọyọ, ti wọn si ti n jẹ mula owo iranwọ naa eyi to n pese ẹgbẹrun kan naira ni fun akẹkọ kan ni taamu kan.
"Ti irinwo akẹkọ ba wa nileewe kan, ta si n pese ẹgbẹrun kan naira fun itọju akẹkọ kọọkan, a jẹ pe ijọba yoo maa na miliọnu lọna irinwo naira ni taamu kan lawọn ileẹkọ girama. Apapọ isiro owo yii yoo si ku si biliọnu kan ati miliọnu lọna igba naira (₦1.2bn) fun saa eto ẹkọ kan fawọn akẹkọ girama."
- Ebi ló ń pami ti mo fi já sọọbu láti jí bisikitì- Afurasi Asuquo
- Ó lé gba ìwé ìrìnnà (Visa) láti wá fẹ̀yìntì sí Naijiria
- Wo aṣọ òtútù tó wọ́n jùlọ ní àgbáyé!
- Tọwọ́ tẹsẹ̀ laá fi gba ìrànwọ́ owó ẹ̀kọ́ Almajiri ní ìpinlẹ̀ Oyo- Alága Subeb
- Buhari kàn ń kọwọ́ bọ̀wé nílẹ̀ òkèèrè kiri ni, a ò rí ipa ní Nàijíríà- Onímọ̀ ọrọ̀-ajé
Ijọba ipinlẹ Ọyọ wa rọ awọn eeyan ti eto yii gberu lawọn ileẹkọ ijọba lati lo owo naa bo se yẹ .
Oríṣun àwòrán, @OfficialSeyiMakinde
Bakan naa lo ni o yẹ ko ye wọn pe ijọba yoo beere nipa bi wọn se naa owo naa, ti yoo si fiya to jogbin jẹ ẹnikẹni to ba gbidanwo lati ya kuro loju opo ilana ipese ojulowo ẹkọ ọfẹ tabi to n dọgbọn gba owo kotọ lọwọ awọn akẹkọ.