Buhari visits Borno: Garba Shehu ní ọ̀pọ̀ èèyàn ló jáde kí ààrẹ káábọ̀, wọ́n ló ṣeun ṣeun

Oríṣun àwòrán, others
Ẹgbẹ́ alátakò ló ràn àwọn èèyàn láti pariwo lé ààrẹ Buhari lori.
Ilé iṣẹ́ ààrẹ orilẹ̀èdè Naijiria ti fẹ̀sùn kan àwọn ẹgbẹ alatako pé, awọn lo san owo láti gba àwọn to kígbe le ààrẹ Muhammadu Buhari lori lasiko ìrìnàjò rẹ̀ lọ si ìpínlẹ̀ Borno lọ́jọ́ru ni.
Oluranlọ́wọ́ pàtàkì àgbà lori igbòhun sáfẹ́fẹ́ fún ààrẹ Buhari Garba Shehu, lo fẹ́sun náà kan lásìkò to n ba BBC sọ̀rọ̀.
- Ta ni wọn yóò búra fún bíi gómínà Bayelsa lónìí, olùdíje PDP ni àbí olórí ilé aṣòfin?
- Ẹ̀ṣọ́ Amotekun ní láti ṣiṣẹ́ pọ̀ pẹ̀lú ọlọ́pàá agbègbè- Ọ̀gá ọlọ́pàá Naijiria
- "Ẹ̀yin obìnrin, ẹ fi òdòdó ṣe ẹ̀bùn ọjọ́ olólùfẹ́ fún ọkùnrin dípò kẹ gbà kó já òdòdó ara yín"
- Ìjọba san ₦200,000 fún Sowore, ó sọ fúnlé ẹjọ́ pé òun kò jẹ̀bi ẹ̀ṣùn
Awọn olùgbé ìlú Maiduguri ti ṣe olúùlú ìpínlẹ̀ Borno pe bo ọkọ ààrẹ lọ́jọ́ru, ti wọn si kígbe ni ìlòdì si ìrìnàjò ààrẹ Buhari lóri ìṣekupani ti àwọn ọlọsa ṣe si àwọn arinrinajo ọgbọ̀n ni Borno.
Shehu ni "Mo wa lára àwọn to rin ìrìnàjo náà láti pápákọ ofurufu titi de ààfin Shehu Borno, àwọn ènìyàn jáde ti wọ́n ki ààrẹ kaabọ, wọn ni o ṣeun fun àbẹ̀wò naa."
Oríṣun àwòrán, Others
"Sùgbọ́n lójìji ni àwọn kan de ti wọ́n bẹ̀rẹ̀ si ni kígbe pe 'A ò fẹ́, A ò fẹ́'
O ní o ṣeeṣe ki àwọn ọlọṣelu ẹgbẹ́ alátako kó àwọn ènìyàn jọ, ki wọ́n si fún wọ́n ni owó láti lọ yẹ̀yẹ́ ààrẹ Buhari"
Gẹ́gẹ́ bi Garba Shehu ṣe sọ, ẹnikẹni to ba ya fọ́nran ibi ti wọ́n ti n pariwo le ààrẹ, to sì tún pin ká lóri ayélujara kò ṣe e láti ràn àwọn ènìyàn ìpínlẹ̀ Borno lọ́wọ́, bi wọ́n ṣe jẹ́ ẹni ti gbogbo ènìyàn mọ gẹ́gẹ́ bi ìlú to maa n gbà alejò.
Valentine: Ọkùnrin ní kí obìnrin má fún àwọn ní àwọ̀tẹ́lẹ̀ mọ́ bíi ẹ̀bùn ọjọ́ olólùfẹ́
O ní ìjọba to n bẹ lóde ti ṣe gudugudu meje, yaya mẹfa láti koju Boko Haram, ti àwọn si ti tun ń pinnu láti yi ìlànà àtẹyinwá pada.