Okada Ban: Bàbá ọmọ ni ₦20,000 péré ni àwọn ọlọ́pàá fi lọ òun àmọ́ òun kò gbàá
Okada Ban: Bàbá ọmọ ni ₦20,000 péré ni àwọn ọlọ́pàá fi lọ òun àmọ́ òun kò gbàá
Arinfẹsẹsi ko kan maili a fi ki ọba oke maa sọ wa.
Baba ọmọdebinrin kan, Mariam Sobukola, ti asita ibọn ba, lasiko iwọde kan to waye lagbegbe Ipaja nilu Eko, lati tako bi ijọba se wọgile wiwa ọkada ati kẹkẹ, ti kigbe tọ BBC Yoruba wa.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ọ̀nà ọ̀tọ̀ ni àjọ EFCC àti NYSC gbé àyájọ́ olólùfẹ́ ọdún 2020 gba
- Ààrùn coronavirus ti ràn dé ilẹ̀ Afirika, Egypt ló kọ́kọ́ yà
- Ìjọba Ọ́ṣun, Oluwo kò yẹ lẹ́ni tó leè darí ìlú, ẹ bá wa le kúrò lórí ìtẹ́ - Olú ti Ilé-Ogbó
- Ọdọọdún làwọn ọmọ ònilẹ̀ ń dà wá láàmú ní Soka, kí Sunday Igboho tó gbà wá sílẹ̀ - Àwọn olùgbé Soka
- Inec kéde pé olùdíje gómìnà fẹ́gbẹ́ PDP ní Bayelsa làwọn gbà pé ó yege ìbò
- Arisekola ló fún mi ní ilẹ̀ tí ìjọba Ọyọ gbẹ́sẹ̀ lé, ń kò ní gbà - Ajimobi
- Ó ṣeéṣe kó má sí ẹ̀ṣọ́ aláàbò Amotekun l‘Eko - Ìjọba Eko
Lasiko to n ba wa sọrọ, Mukaila Sobukola ni awọn ọlọpa to yinbọn mọ ọmọ oun ko tiẹ tara nipa isẹlẹ naa rara, oun nikan si ni oun n da gbọ bukata wahala yii.
Sobukọla ni dokita yọ ọta ibọn lara ọmọdebinrin naa, to si fi le oun lọwọ, amọ o ni, lọjọ kẹta ni dokita tun n bẹ oun pe ki oun mu ọta ibọn naa wa pada, ti wọn ko si fun oun mọ.
O fikun pe ọlọpa obinrin kan yọju si awọn sile iwosan, to si na ẹgbẹrun lọna ogun naira si awọn, amọ oun ko gbaa lọwọ rẹ, lati igba naa wa, awọn ko gbọ ohunkohun mọ.