Osogbo JTF vs Youth Protest: Àwọn ẹbí Idris Ajibola ń fẹ́ ìdájọ́ lórí ikú ọmọ wọn
"Iku ẹ ko gbọdọ lọ lasan o, gbogbo awọn to wa nidi ẹ, mo fi wọn si ọwọ Ọlọrun".
Temitope, ẹgbọn Idris Ajibola ti ikọ amuṣẹya alaabo niluu Osogbo le oun atawọn ọrẹ rẹ de oju iku faraya.
Ọjọ kẹẹdogun oṣu kẹsan ọdun 2020 ni Idris salabapade iku.
BBC Yoruba ṣe ibẹwo si idile ti ọfọ ṣẹ yii niluu Osogbo nibi ti ẹsẹ ko ti gbero gẹgẹ bi awọn eeyan ṣe n wọ lati lọ bawọn kẹdun iku ọmọ wọn.
Ọ̀rọ̀ gbogbo ṣe wọn maa n ni Ọlọrun lo ye - Ọtọ lọrọ tawọn ọlọpaa sọ ọtọ la ba lẹnu awọn mọlẹbi Idris.
- Àwòrán òkú ọmọ mi ni mo kọ́kọ́ rí lójú òpó ayelujara - Bàbá ọmọ tí SARS lé dójú ikú
- Wo ọ̀rọ̀ Fani-Kayode sí akọ̀ròyìn "blog" tó ní lílù ìyàwó rẹ̀ bíi bàrà ló mú wọn túká
- Adunni Oluwole, akọni obìnrin tó tako òmìnira Nàìjíríà, ó ní òyìnbó kò gbọ́dọ̀ lọ
- Kí ni apẹ̀rẹ̀ ikòlẹ̀sí Eko fi yàtọ̀ sí ti Ekiti tí ọ́ọ́físà mú wa mọ́lẹ̀?
- Njẹ́ o mọ̀ pé bíi ọdún 700 sẹ́yìn ni wọ́n ti ń bọ Osun-Osogbo? Mọ̀ síi nípa ìtàn ojúbọ̀ nàá
- Ǹjẹ́ o mọ̀ pé àwọn tó wá láti ìdílé ẹrú kìí lọ́kọ tàbí aya láyé òde òni ní Nàìjíríà?
- Ọdún méjì, wàhálà méjì lójúbọ Osun Osogbo,
Ṣaaju ni baba ọmọdekunrin naa arakunrin Kehinde Ajibola sọ pe ọmọ oun kii ṣe oni yahoo yahoo ati pe iwa aibọwọ fofin lawọn agbofinro to ṣeku pa ọmọ naa hu.
Ẹgbọn rẹ ọkunrin to ba BBC Yoruba sọrọ sọ pe "ọmọ tiwa ko ki n ṣe yahoo boy o, amojuẹrọ ni ọmọ wa to si ti n ṣiṣẹ titun foonu ṣe latigba to ti pari ileewe".
O ṣalaye pe ṣaadede loun gba ipe lọjọ naa pe wọn ti pa aburo oun ti wọn si ti lọ t oku rẹ siwaju ọfiisi gomina ipinlẹ Osun, Gboyega Oyetola.