Apam Beach Drowning: Wọ́n ti sin òkú àwọn akẹ́kọ̀ọ́ mẹ́ẹ̀dógún náà lápapọ̀

Bi eeyan ba jẹ ori ahun, yoo sọkun to ba gbọ iroyin nipa iku awọn akẹkọ bii ogun, ti wọn ls luwẹ ni eti okun Apam lọjọ Aiku, ọjọ Keje osu Kẹta ọdun 2021.
Ileesẹ ọlọpaa nilẹ Ghana ti wa fidi rẹ mulẹ pe awọn ti ri oku mẹtala lara awọn akẹkọ naa to ku sinu okun ti wọn ti n luwẹ letikun Apam lọjọ Aje, ọjọ Kẹjọ osu Kẹta.
Atẹjade kan ti ileesẹ ọlọpaa ni Ghana fisita salaye pe meji ninu awọn akẹkọ naa ni wọn ri laaye leti okun ọhun, nigba ti wọn ri oku akẹkọọ mejila.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Bí Buhari kò bá ṣọ́ra, àwọn ọba alayé ni yóò ṣaájú ìjìjàgbara fún Yorùbá - Sunday Igboho
- Gómìnà Yorùbá, ẹ lo ààbò lábẹ́lé láti ṣọ́ ìpínlẹ̀ yín, ẹ má gbára lé ọlọ́pàá - Afenifere
- Ẹ dáábò bo ara yín, a kò le ṣọ́ gbogbo ilé ẹ̀kọ́ Nàíjíríà - Ìjọba àpapọ̀ lahùn
- Ohun tó ṣe mi rèé nígbà tí mo gba abẹ́rẹ́ àjẹ́sára AstraZeneca - Kọ̀misáná fétò ìlera l‘Eko
- Níbo ní £46,933 owó ìrànwọ́ tí wọn dá fún Sunday Igboho wa?
- Ẹ mú ẹ̀rí tó dájú wá lórí ọ̀rọ̀ Fulani darandaran Wakili, ọlọ́pàá rọ àwọn èèyàn ìpínlẹ̀ Oyo
- Wo àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ti fà kalẹ̀ fún àmì ẹ̀yẹ Grammy tẹ́lẹ̀ rí
- Iṣẹ́ ti bẹ̀rẹ̀ láti dóòlà akẹ́kọ̀ọ́bìnrin méjì Fásítì Olabisi Onabanjo táwọn agbébọn jígbé- Ọlọ́pàá
- Asari Dokubo tó kéde orílẹ̀èdè Biafra lu òfin ìdìtẹ̀ sí orílẹ̀-èdè - Àgbà Amòfin
- Ọwọ́ mi dẹ púpọ̀ ní Ayete, n kò kéde lórí ayélujára ní – Sunday Igboho
Ọga ọlọpaa Irene Oppong to wa ni ẹka to n gbọ ọrọ araalu nilu Cape Coast ni ọkunrin kan, Kwame Akono lo mu ẹsun nipa isẹlẹ naa tọ oun wa.
"Deede aago mẹsan ku ogun isẹju ni ọkunrin naamu ẹsun tọ wa wa pe ọmọ ẹgbọn oun, Joshua Annor, tii se ọmọ ọdun mẹẹdogun lo lọ gba bọọlu leti okun, to si ri sinu rẹ pẹlu awọn ọmọ miran.
Idi niyi ta fi tete morile eti okun naa pẹlu ikọ ti yoo wa awọn ọmọ naa jade, Ọlọrun si ba wa se, a ri Simon Dadzie, ọmọ ọdun mẹẹdogun ati Gogffrey Apperetsie, ọmọ ọdun mẹrinla yọ laaye."
Oppong fikun pe awọn akẹkọ mejeeji yii lawọn tete gbe lọ sile iwosan ijọ Aguda ti Luke fun itọju to yẹ.
Akomolede àti Asa: Mọ̀ si nípa àṣà ìsọmọlórúkọ́ nílẹ̀ Yorùbá àti ìtumọ̀ orúkọ̀ fún ìkókó
O ni awọn oku awọn akẹkọọ tawọn ri ni aarọ ọjọ Aje ni ọjọ ori wọn wa laarin ọdun mẹrinla si mẹtadinlogun, ti oku ọmọbinrin meji si wa laarin wọn.
O ni awọn oku awọn ọmọbinrin mejeeji naa lawọn gbe lọ sile igbokusi to wa nile iwosan fun ayẹwo to yẹ, ti iwadi si ti n lọ lọwọ lati mọ iru iku to pa awọn akẹkọ naa.
Adebunmi Adeyeye: Mo jẹ gbèsè gbọ́múléláńtà, ìdí iṣẹ́ kabúkabú ni mo ti ri san
Amọ sa, wọn ti sin oku awọn akẹkọ mẹtala ọhun lapapọ loni ọjọ Isẹgun, kutu hai si lawọn mọlẹbi wọn ti de sile iwosan katoliki Luke nibi ti wọn gbe oku awọn ọmọ naa si.