Seyi Makinde: Tí aráàlú bá kọ̀ mí bíi gómìnà, ẹ̀rù kò bà mí láti fipò sílẹ̀

Oríṣun àwòrán, Facebook/Seyi Makinde
Gomina ipinlẹ Oyo, Onimọ ẹrọ Seyi Makinde ti kede pe ko le tu iru kan lara oun, ti oun ba kuna lati bori ibo fun saa keji.
Makinde lo ti kuna fun igba mẹta ọtọọtọ to tiraka lati di ibo gomina ipinlẹ Oyo eyi to waye lọdun 2007, 2011 ati 2015.
Gomina Makinde lo sisọ loju ọrọ yii nibi ipade awọn alẹnulọrọ lori eto aabo ilẹ Yoruba to waye ni gbọngan Mapo nilu Ibadan lọjọru.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- A ń lọ ṣí ẹnu bodè Yorùbá tíjọba tìpa sílẹ̀, kí oúnjẹ wọlé nírọ̀rùn - Sunday Igboho
- Ẹyọ kan lára agbára tí mo ní, ni mo lò láti mú Wakili - Gani Adams
- A kọ òrìṣà babańlá wa sílẹ̀ ló jẹ́ kí ọ̀daràn darandaran máa pa wá bí ẹ̀fọn - Àwọn Oníṣẹ̀ṣe
- Ìtàn ayé John Magufuli, Ààrẹ Tanzania tọ́pọ̀ èèyàn ń pè ní 'bulldozer'
- Wo ohun tí o kò mọ̀ nípa Ààrẹ Tanzania, John Magufuli tó jáde láyé
- Wo ewu tó rọ̀ ma kí wọn sin ọba tó ṣètùtù nílànà ẹ̀sìn Krìsítẹ́nì àti Islam
O tun fikun pe oun setan lati kuro lori aleefa tawọn araalu ba ni ki oun maa lọ, ru ko si ba oun lati fi ipo gomina silẹ.
"Ti awọn eeyan ipinlẹ Oyo ba ni ki n kuro ni ọọfisi gẹgẹ bii gomina ipinlẹ Oyo, n ko ni ro ni ẹẹmeji, ki n to kuro nitori ojoojumọ ni mo n gbe baagi mi lọ si ọọfisi lati ile."

Oríṣun àwòrán, Facebook/Seyi Makinde
Bakan naa ni gomina Makinde ni oun ko ni baba isalẹ ninu oselu, Ọlọrun si lo sọ oun di gomina, kii se ẹda alaaye kankan.
"Ọlọrun nikan ni mo bẹru, n ko bẹru ẹda alaaye kankan, ko si si bi ẹda kan se ni agbara to, emi ko le e bẹru rẹ.
Mo dije fun ipo gomina lọdun 2007,2011 ati 2015, ti mo si ja kulẹ amọ nigba ti Ọlọrun ni akoko to lati sọ mi di gomina, o gbe mi de ipo naa."
Makinde ni oun ko ni abẹrẹ ni ọọfisi ti oun le boju wo lẹyin, ti ilọ ba ti ya, oun ti setan."
O fikun pe ijọba oun ti n pese aabo to peye lati daabo bo ẹmi ati dukia, ti ijọba oun yoo si tun se amulo awọn ara ita lẹka eto aabo rẹ.
Farmers Herders Crisis: Rẹ́rẹ́ rún, ẹ̀mí àti dúkìá ṣòfò lágbègbè Ariwa Yewa
"Nitori ipo ti mo wa, awọn ohun ti mo n ri, ẹyin ko le ri i, mo si n seleri pe ma maa se ipinnu nibamu pẹlu ifẹ araalu ni."
O wa sisọ loju rẹ pe nibi ipade eto aabo to kọja, oun da aawọ silẹ nitori pe eto aabo to mẹhẹ ti kọja ka maa fi ẹnu pa a lasan.
O ni awọn eeyan ti ko ba si lara awọn osisẹ ikọ alaabo Amotekun le lọ di ara ikọ ọdẹ ibilẹ Soludero tabi Fijilante gẹgẹ bi ara ọna lati fi ara wọn silẹ fun isẹ aabo ilu.
Àwọn agbébọn jí èèyàn méjì gbé ní ibùdó tí wọ́n tí ń fọ́ òkúta ní Ibadan

Oríṣun àwòrán, Facebook/Seyi Makinde
Saaju la ti sọ fun yin pe awọn eeyan meji ọtọọtọ ni awọn agbebọn ji gbe l'ọjọ Aje ni ibudo ti wọn ti n fọ okuta kan to n bẹ nilu Ibadan.
Ọkan ninu awọn eeyan meji naa jẹ oṣiṣẹ ileeṣẹ abanikọle, RCC ti ẹnikeji si jẹ oṣiṣẹ ile ifowopamọ Polaris.
Ijinigbe naa ṣẹlẹ lasiko ti awọn agbebọn yawọ ibudo ti wọn ti n fọ okuta(Binu Quarry) to n bẹ ni ilu Dalli lopopona Ibadan si Ijẹbu-Ode lati gbe awọn eeyan meji naa.
- Wakili àtàwọn méjì míì dèrò ẹ̀wọ̀n lẹ́yìn tí wọ́n fẹ̀sùn ìpànìyàn, ìjínigbé àti olè kàn wọ́n
- ''Nítorí N20, ọlọ́pàá yìnbọn fún mi lọ́rùn, mi sì ò lè b'óbìnrin lọ̀pọ̀ mọ́ bímọ''- Fagbemi
- Agbẹnusọ Sunday Igboho ná N2.5m bíí owó oúnjẹ́ lásán, gbas gbos bẹ̀rẹ̀
- Akẹ́kọ̀ọ́ ogún lọ lúwẹ̀ẹ́ léti òkun, 15 kú, mẹ́ta pòórá, méjì yè
- Bí ìjọba, ọlọ́pàá, ológun, Amotekun ò bá le gbà wá, àwa mú Wakili láti gba ìran Yorùbá sílẹ̀ ni - OPC
- Wo nkan tó yẹ kí o mọ̀ nípa Iskilu Wakili, afurasí Balógun Fulani tí OPC mú ní Ayetẹ ìpínlẹ̀ Ọyọ
Iroyin fi idi ẹ mulẹ wi pe wọn ti fi ọrọ naa to awọn ọlọpaa agbegbe Idi Ayunrẹ leti nilu Ibadan.
Ijinigbe yii waye lẹyin oṣu diẹ ti awọn agbebọn yawọ ibudo ti wọn ti n fọ okuta kan ni agbegbe ijọba ibilẹ Akinyẹle, ti wọn si ji awọn oṣiṣẹ kan gbe lọ.
Alukoro ajọ ọlọpaa nipinlẹ Ọyọ, Arakunrin Olugbenga Fadeyi fi idi iṣẹlẹ naa mulẹ.
L'ọjọ Iṣẹgun ni Fadeyi ṣe alaye wi pe ileeṣẹ ọlọpaa ti n sa gbogbo ipa lati ri i daju wi pe awọn eeyan naa gba ominira.