Gani Adams: Gbogbo gómìnà Yorùbá ni mo kọ̀wé sí láti bá ṣèpàdé

Oríṣun àwòrán, Twitter/Seyi Makinde
Ni itẹsiwaju ọna ati wa ojutu si awọn ipenija to n koju ilẹ Yoruba, Aarẹ Ọna Kakanfo Gani Adams ati Gomina Seyi Makinde ti dijọ ṣepade pọ nilu Ibadan.
Ipade yi ti wọn ṣe ni bonkẹlẹ la gbọ pe o da lori ọrọ aabo ati ọrọ aje ilẹ kaarọ o jiire.
Atẹjade lati ọdọ agbẹnusọ feto iroyin fun gomina Seyi Makinde, Ọgbẹni Taiwo Adisa sọ pe aarẹ Gani Adams lo kọwe si gbogbo awọn Gomina ipinlẹ Yoruba lati beere fun ipade lori ọrọ aje ati aabo.''
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ẹyọ kan lára agbára tí mo ní, ni mo lò láti mú Wakili - Gani Adams
- Sunday Igboho ṣẹ̀ sí òfin ète ìdìtẹ̀ gbàjọba, ó sì le fojú winá òfin - Amofin
- Bí ọlọ́pàá bá tó bẹ́ẹ̀, kó dá wa lọ́nà, Yoruba kìí ṣe ara Naijiria mọ́ - Sunday Igboho
- Ẹ gbọ́ ná, kí ló lè mú kí àfín 114 di àwátì?
- Afurasí olóṣèlú tí ọlọ́pàá mú lórí ikú ọmọ mi, ló jẹ́ alátakò rẹ̀ nínú PDP - Baba Aborode
- Jimoh Odutola, akọni oníṣòwò tí kò kàwé, àmọ́ táwọn Ààrẹ orílẹ̀-èdè ń ké sí láti wá dá iléesẹ́
- Akẹ́kọ̀ọ́ kò yọjú sílé ẹ̀kọ́ lẹ́yìn tí àwọn olùkọ́ padà sẹnu iṣẹ́ nílèèwẹ tí rògbòdìyàn Hijab ti wáyé n'Ilorin
Gani Adams ninu ọrọ rẹ si ni ''Inu mi si dun pe wọn jẹ mi ni o''
Iba tẹsiwaju pe ''mo ṣepade pẹlu Gomina Ekiti ni ọjọ meji sẹyin, nibayi mo n ṣe ipade pẹlu Gomina Oyo''
Oríṣun àwòrán, Facebook/Seyi Makinde
O ni o ṣe pataki kawọn fikunlukun lori ọrọ iṣẹ agbẹ ati pe, awọn Gomina mejeeji ti sọ ọna tawọn yoo fi mu idagbasoke ba iṣẹ agbẹ, paapa fawọn aladani.
''Mo fẹ fi da wọn loju pe awa naa yoo kopa tiwa lati ri pe a mọ awọn to fẹ dowo pọ pẹlu wọn wa''
Iba Gani Adams tun fikun ọrọ rẹ pe, ati awọn ati ijọba Oyo, ibi kanna lawọn jijọ n foju sun lori mimu alaafia ba ara ilu.
Ogbomoso Quitdruplets: Ọ̀kan nínú àwọn ìbarùn-ún jáde láyé lọ́jọ́ karùn-ún
O ni pẹlu ibi ti ọrọ de yii, awọn ọmọ Yoruba ko gbọdọ sun asunpiye, o si yẹ ki wọn pawọpọ lori ọrọ aabo ilẹ wọn eyi to ni ojuṣe gbogbo ọmọ Yoruba nii ṣe.