NDA Kaduna attack: Ẹ̀yin akọ̀ròyìn, ẹ má sọ ọ̀rọ̀ wa láì dá a mọ́ - Iléèṣẹ́ ológun

Oríṣun àwòrán, BASHIR AHMAD/FACEBOOK
Ẹka to n mojuto eto iroyin nileeṣẹ ologun Naijiria, ti bẹ awọn akọroyin pe ki wọn o ma sọ ọrọ ileeṣẹ ologun lọna ti ko dara.
Eyi waye lẹyin ọjọ kẹta ti awọn agbebọn ti ẹnikẹni ko mọ, kọlu ile ẹkọ awọn ologun, Nigerian Defence Academy (NDA), nilu Kaduna, ti wọn si pa
Lati igba ti iṣẹlẹ naa ti waye ni awọn ọmọ Naijiria ti n beere oriṣiriṣi ibeere lọwọ ileeṣẹ ologun.
- Wo iye ìgbà tí wọ́n ti jí akẹ́kọ̀ọ́ gbé ní Nàìjíiríà
- Ìkọlù sí NDA yìí ní yóò múṣẹ́ yá lórí fífi òpin sí ìwà ọ̀daràn ní Nàìjírà-Ààrẹ Buhari
- "Ó yẹ kí àwọn ẹ́ṣọ́ aláàbò lè mọ̀ pé àwọn jàndùkú fẹ́ kọlu ilé ẹ̀kọ́ ẹ̀kọ́ṣẹ́ ọmọogun Nàìjíríà, NDA kí ìṣẹ̀lẹ̀ náà tó wáyé"
- Èèyàn márùn ún kú, ọ̀pọ̀ míì farapa lásìkò rògbòdìyàn àwọn ọmọ onílẹ̀ l'EKo
Ti oriṣiriṣi iroyin si n jade nipa iṣẹlẹ naa.
Oludari ẹka iroyin nileeṣẹ ologun, Ọgagun Benjamin Olufemi Sawyerr fi ọrọ ẹbẹ naa sita ni ori redio Voice of Nigeria, ati Federal Radio Corporation of Nigeria, FRCN, lọjọru, ọjọ kẹẹdọgbọn, oṣu Kẹjọ.
Oríṣun àwòrán, DIRECTORATE OF DEFENCE INFORMATION
Ọgagun Sawyerr sọ pe ki awọn ileeṣẹ iroyin fọwọsowọpọ pẹlu ileeṣẹ ologun, ki wọn o si ma a gbe iroyin to ba dara jade nipa ileeṣẹ ologun, fun idagbasoke ati alaafia orilẹ-ede Naijiria.
Ondo Jos clash: Èmi nìkan ló padà dé nínú àwa márùn ún tí a jọ lọ ìpàdé àdúrà ní Jos- Bell
Ṣugbọn ṣa, Agbẹnusọ fun Aarẹ Muhammadu Buhari, Garba Shehu, sọ pe igbiyanju lati fi iṣejọba Aarẹ Buhari ṣe ẹlẹya, ni nkan to ṣẹlẹ ni ileeṣẹ ologun.
Rape survivor: Ìyá mi ni ń kò gbọdọ̀ sọ̀rs kí ilé má bà á dàrú- Oluwatobi Raji
Garba Shehu sọ pe iṣẹlẹ naa bani lọkan jẹ.
Ọjọ kẹrinlelogun, oṣu Kẹjọ, ni ile ẹkọ ologun naa fi atẹjade sita pe awọn agbebọn kọlu ile ẹkọ naa, to wa ni Afaka, Kaduna.
Oríṣun àwòrán, DIRECTORATE OF DEFENCE INFORMATION
Awọn agbebọn naa wọ ibugbe awọn ọmọ ogun, ti wọn si pa eeyan meji. Wọn tun ji ẹnikan gbe lọ.
Ọjọ keji iṣẹlẹ naa si ni iroyin jade pe oju orun ni awọn ọmọ ogun to n mojuto ẹrọ ayaworan CCTV to wa ninu ọgba naa wa nigba ti ikọlu ọhun waye.
Ṣugbọn, ileeṣẹ ologun sọ pe irọ ni iroyin naa.
- Kò sí ọmọ Zambia kan tó má sùn pẹ̀lú ebi mọ́ lásìkò tèmi gẹ́gẹ́ bíi Aàrẹ- Hichilema ṣèlérí
- "Ó yẹ kí àwọn ẹ́ṣọ́ aláàbò lè mọ̀ pé àwọn jàndùkú fẹ́ kọlu ilé ẹ̀kọ́ ẹ̀kọ́ṣẹ́ ọmọogun Nàìjíríà, NDA kí ìṣẹ̀lẹ̀ náà tó wáyé"
- Ilé ẹjọ́ wọ́gilé ẹ̀bẹ̀ DSS láti dáwọn ọmọlẹ́yìn Sunday Igboho mẹ́rin tó gb'òmìnira padà s'atìmọ́lé
- Wo ìgbésẹ̀ tí ìjọba ìpínlẹ̀ Plateau gbé lẹ́yìn ìkọlù tó wáyé lónìí
- Ìkọlù sí NDA yìí ní yóò múṣẹ́ yá lórí fífi òpin sí ìwà ọ̀daràn ní Nàìjírà-Ààrẹ Buhari
Unijos students victims: Àwọn Fulani yabo 'hostel' wa, ọpẹ́lọpẹ́ àwọn Sọ́jà tí gómìnà ìpí