Anti Open Grazing Law: Àwọn èèyàn gúúsù ń fi ọ̀rọ̀ ránṣẹ́ padà sí El-Rufai lórí àtakò òfin

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Alaga awọn gomina apá guusu Naijiria, Rotimi Akeredolu ti koro oju sí gomina ipinlẹ Kaduna, Nasir El-Rufai lori bi o ṣe tako fifi ofin de idẹranjẹko lẹkun guusu.
Akeredolu ni ọgbọn ati ko awọn janduku ajínigbé wọ apá guusu ni El-Rufai ń da.
El-Rufai ti kọkọ tabuku bi awọn ipinlẹ apá guusu ṣe ṣ'agbekalẹ ofin tó dé idẹranjẹko ni gbangba.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Wo èèwọ̀ mẹ́wàá to fi lè bọ́ lọ́wọ́ ewu iná gáàsì
- Ìjọba ẹ má wòran, àjà ilé Aṣòfin tó ń jò le wó lé wa lórí - Aṣòfin sọ̀rọ̀ ṣókè!
- Ondo School Without Chairs: Iléèwé kan rèé tí kò ní àga, tábìlì, olùkọ́ àti ohun èèlò ìkẹ́kọ̀ọ́
- Tá à bá ti ibodè tó wọ Naijiria, ìyà kò bá jẹ wá lásìkò Coronavirus - Buhari
- Ọ̀run yóò ya bọ́ tí ààrẹ kò bá wá láti ẹ̀kùn gúúsù Nàíjíríà - Joe Igbokwe
- Kí ló ń fa ikú ọ̀wọọ̀wọ́ lẹ́yìn Davido?
- Ààrẹ tẹ́lẹ̀, Goodluck Jonathan ti sọ̀rọ̀ sókè, Ó ní wàhálà Nàìjíríà fẹ̀rẹ̀ gbẹ̀mí ìyá òun
Àmọ́, Akeredolu sọ ninu atẹjade kan ti kọmiṣọnna eto iroyin nipinlẹ Ondo fi sita pe iru ẹni to ba sọrọ ti El-Rufai sọ ko yẹ nipo olori.
Gomina ipinlẹ Ondo sọ pe El-Rufai ń wa ọna lati ko awọn janduku ajinigbe pawo afẹmi ṣofo lọ si ibo miran lẹyìn awọn ologun ti n fina mọ wọn bayii lapa Ariwa Naijiria.
Akeredolu fikun ọrọ rẹ pé irú ọrọ ti El-Rufai sọ yìí lè dá rogbodiyan silẹ laarin ilu.
Ondo School Without Chairs: Iléèwé kan rèé tí kò ní àga, tábìlì, olùkọ́, èlò ìkẹ́kọ̀ọ́
Gomina ipinlẹ Ondo ni fifi ẹran jẹko káàkiri ilu ti di eewọ bayii lapa guusu Naijiria, kò sì sí ohun tí ẹnikẹni le ṣe sí ọrọ naa.
Akeredolu ni awọn ti ko dun mọ kí wọn lọ fọwọ wọnu nitori aṣẹ ti gùn ofin tó dé idẹranjẹko ni gbangba lapa guusu Naijiria.
Ẹgbẹ̀rún mẹ́jọ agbébọn Boko Haram ló ti jọ̀wọ́ ara wọn sílẹ̀- Iléeṣẹ́ ológun
Oríṣun àwòrán, Facebook/NigerianArmy
Ọgagun agba ọwọ keje ileeṣẹ ọmọogun Naijiria, Ọgagun Abdulwahab Eyitayọ ni ẹgbẹrun mẹjọ lawọn ọmọogun agbesunmọmi Boko Haram to ti jọwọ ara wọn fun awọn ologun bayii.
O ni awọn agbebọn naa jọwọ ara wọn sílẹ lati inu ibuba wọn ni igno Sambisa atawọn ibuba miran.
- Wo ohun tó yẹ ko mọ̀ nípa Saheed Adigun (Adogan) tó kú nílé Sunday Igboho
- "DSS yin ọta ìbọn 48 sí Adogan, kò sì kú, ni wọn bá fi ọmọ odó fọ lórí"
- Sunday Igboho ń dáró èèyàn kejì tí DSS pa nílé rẹ̀
- "Alhaji Fatai, ti DSS pa nílé Sunday Igboho ni kò ríran"
- Sunday Igboho ń ṣọ̀fọ̀ ọ̀kan lára àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ tí DSS pa
- DSS kò mú mi lọ́dọ̀ Guru Maharaji, èmi rèé n‘Ibadan, ẹ sinmi àhesọ ọ̀rọ̀ -
Ọgagun Eyitayọ to tun jẹ ọgagun agba igun kini, Sector 1 Operaton Hadin Kai ṣalaye eyi lasiko to n gnalejo alukoro ileeṣẹ omogun oriilẹ ni Naijiria, ogagun Onyema Nwachukwu atawọn akọroyin lalejo nilu Maiduguri.
Hijab Female Footballer: Zulfah ní àlá òun ní láti jẹ́ agbábọ́ọ̀lù obìnrin tó dáńtọ́
Ogagun naa ni ohun ayọ ni bi awọn agbebọn naa ṣe n jọwọ ara wọn silẹ ati pe bi awọn ologun ṣe n kona mọ wọn lo n ti wọn sita.
Ọgagun Eyitayọ fi kun pe lọpọ yanturu lawọn agbebõn Boko Haram n jọwọ ara wọn sílẹ lati igba tawọn ọmọ ogun ṣina ibọn fun wọn.
- Ìkọlù DSS sílé Sunday Igboho tàpá sófin, ìwà ìjọba ológun ni - Falana
- Ìbọn àti nǹkan ìjagun ni Igboho kó pamọ sílé ló jẹ kí á yabo ilé rẹ̀ - DSS
- Sunday Igboho, ìsáǹsá rẹ̀ kò lé sá mọ́ wa lọ́wọ́, mímú lá mú ọ - DSS fọwọ́ gbáyà
- Ó tó gẹ́, Sunday Igboho fẹ́ gbé ìjọba lọ ilé ẹjọ́ bí wọn kò bá tú àwọn èèyàn rẹ̀ sílẹ̀
Ogagun naa ni pupọ awọn agbebọn naa lo jẹ pe igbaye gbadun awọn ẹbi wọn lo ṣokunfa bi wọn ṣe darapọ mọ awọn agbebọn naa.
O wa sekilọ pe eyikeyi awọn agbebọn naa ti ko baa jọwọ ara rẹ silẹ ki gbendeke ọjọ ti wọn fi silẹ fun wọn, yoo jẹ iyan rẹ niṣu ti ko si ni yọ awọn agbodegba ati baba isalẹ wọn pẹlu silẹ.
Oríṣun àwòrán, Facebook/NigerianArmy
Ọgagun Eyitayọ to tun jẹ ọgagun agba igun kini, Sector 1 Operaton Hadin Kai ṣalaye eyi lasiko to n gnalejo alukoro ileeṣẹ omogun oriilẹ ni Naijiria, ogagun Onyema Nwachukwu atawọn akọroyin lalejo nilu Maiduguri.