Sunday Igboho: Gómìnà Akeredolu fi ìdánilójú hàn pé Sunday Ìgbòho Yóò Padà Sílé Láyọ̀ àti Àlááfíà

Gomina ipinlẹ Ondo, Arakunrin Oluwarotimi Akeredolu ti fi idaniloju re han pe, ajijangbara fun idasilẹ orilẹ ede Yoruba, Sunday Adeyemo ti gbogbo eniyan mọ si sunday Igboho yíò pada si'ile l'ayọ
ati alaafia.
Akeredolu sọ ọrọ yi nigba ti o n ba awọn oluwọde fun itusilẹ Sunday Igboho sọrọ ní ọfiisi rẹ ni ilu Akurẹ.
Gomina ọun ti akọwe ijọba, ọmọbabirin Oladunni Odu ṣoju fun sọpe ọmọ Yoruba rere ni Igboho ti nkankan ko gbọdọ ṣe.
- Ilé ẹjọ́ ti pàṣẹ tuntun fún ọ̀ga ọlọ́pàá Nàìjíríà lórí Rahmon Adedoyin tí Timothy Adegoke kú sí ilé ìtura rẹ̀
- Wo ìdí tí Sanwo-Olu ṣe wọ́gilé ìrìn àláàfíà 'Walk for Peace' tó fẹ́ẹ̀ rìn pẹ̀lú àwọn ará Eko
- Fadeyi Oloro wà ní ìdúbúlẹ̀ àìsàn, ẹ jọ́wọ́ ẹ rànwá lọ́wọ́ - Foluke Daramola
- 2022 Hajj: Saudi fòfin de ìrìn-àjò bàálù láti Nàìjíríà torí ẹ̀dà covid-19 Omicron
- Ìlú Eko yóò gbàlejò Àarẹ Muhammadu Buhari lónìí
Owa dupẹ lọwọ awọn oluwọde naa fun gbigba alaafia laaye latari iwọde wọn pẹlu idaniloju pe ohun koni di ẹnikẹni lọwọ lati ṣe iwọde ti ko ni jagidijagan ninu.
Siwaju, ọgunlọgọ eniyan labẹ asia ẹgbẹ ọmọ Yoruba ni wọn ti ṣe iwọde ni ilu Akure fún itusile Igboho ti wọn si rin lati agbegbe Old-Garage lọ si ile iṣẹ gomina ti ipinlẹ Ondo.
Awọn oluwọde naa ti ọgbẹni Victor Omojowo gbẹnusọ fun ni wọn rọ Akeredolu ko lo ipo ẹ gẹgẹ bi adari awon gomina ni iwọ oorun Nigeria lati ripe Igboho o ṣe odun keresimesi ni ihamọ ijọba Benin
Republic.O fikun ọrọ rẹ pe nitori alaafia ni awọn duro le lori, awọn agbofinro ko gbọdọ halẹ mọ won.
Awọn to kopa ninu iwode naa ni wọn wa lati ijoba ipinle mejeejidinlogun ti o wa ni ipinle Ondo.
KieKie