Silas Adekunle: Ó tún sẹ̀sẹ̀ fọwọ́sí àdéhùn alàìmọye mílíọ́nù dọ́là

Oríṣun àwòrán, Forbes
Lẹyin ti Adekunle pari eto ẹkọ girama rẹ nilu Eko, lo tẹ ọ̀kọ leti lọ soke okun fun eto ẹkọ fasiti rẹ
Silas Adekunle, tii se ọmọ Yoruba lati ipinlẹ Eko, ni onimọ ẹrọ to n se ‘Ẹrọ-deniyan’, taa mọ si ‘Rọbọti’, to n gba owo to pọ julọ ni ilu ọba.
Iroyin kan fi ye wa pe koda, Adekunle tun ti fọwọsi iwe adehun kan fun sise Rọbọti, eyi ti owo rẹ to aimọye miliọnu dọla.
Koda ikọ kan ti wọn n pe ni Black Hedge Fund Group ti figbe ta pe Adekunle ni ẹni naa ti oju gbogbo yoo maa wo lọdun 2018 lẹka imọ ẹrọ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Àṣìlò òògùn burú, ṣùgbọ́n ṣé ẹ̀bi ará ìlú nìkan ni?
- Sunday Igboho, Akintoye àtàwọn míràn fa Buhari, Malami àtàwọn míì lọ síwájú ilé ẹjọ́ àgbáyé ICC
- Ọmọ Naijiria 350 ni ẹ̀mí wọn sọnù nínù ìjàmbá ọkọ̀ ojú omi lọ́dún 2020
- Olórí ilé asòfin l‘Ọ́sun pàdánù N38m sọ́wọ́ gbájúẹ̀
- Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ ọkùnrin tó gbé ọ̀kadà iléesẹ́ sá lọ lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta tó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́
- A ti bẹ̀rẹ̀ ìwádìí lórí ẹ̀sùn tí Igboho, Akintoye àti Ilana Omo Oodua gbé wa síwájú wa- ICC
Lẹyin ti Adekunle pari eto ẹkọ girama rẹ nilu Eko, lo tẹ ọ̀kọ leti lọ soke okun fun eto ẹkọ fasiti rẹ, ni University of West England.
Adekunle kẹkọjade nile ẹkọ fasit naa, to si jade pẹlu iwe ẹri isọri akẹkọ kinni to yege, taa mọ si First Class ni ẹka imọ nipa sise ẹrọ deniyan rọbọti, lẹyin eyi lo wa da ileesẹ tara rẹ silẹ, eyi to n se ẹrọ Rọbọti.
OsunDecides: Omisore ní ẹni tó bá fẹ́ ra ìbò, àwọn yóò lọ lásọ mú ni
Lọdun 2017, nigba to wa nileesẹ MekaMon, ni Adekunle se agbekalẹ Rọbọti akọkọ rẹ eyi tii se Rọbọti akọkọ fun ere idaraya, ti ẹrọ naa si lee sisẹ bii eniyan. Ẹẹdẹgbẹta ẹrọ yii ni awọn eeyan du ra, eyi to pa miliọnu mẹtadinlogun ati aabọ dọla wọle.
Oríṣun àwòrán, Getty Images
Adekunle se agbekalẹ Rọbọti akọkọ rẹ eyi tii se Rọbọti akọkọ fun ere idaraya
Aseyọri yii lo mu ko ri oniruuru atilẹyin gba lati ọdọ awọn ileesẹ nla-nla, to fi mọ ileesẹ London Ventures Patners, ti wọn fun ni miliọnu mẹwa dọla ($10m) lọdun naa. Bakan naa ni ileesẹ rẹ Reach Robots fọwọsi iwe adehun pẹlu ileesẹ Apple lati jẹ ojulowo alagbata fawọn ẹrọ́-deniyan naa.
'Èmi gan máa ń béèrè lọ́wọ́ ara mi pé ta ni Wole Soyinka gangan'
Isẹ ọna to sọnu ni Naijiria di riri loke okun
Ninu Iroyin mi i ẹwẹ, isẹ ona ilẹ Naijiria kan to ti nu tipẹtipẹ lo sadede suyọ ni filati onile kẹjẹbu kan ni ariwa ilu London.
Isẹ ọna naa, to jẹ aworan Ọmọọba Adetutu Ademiluyi lati Ile Ife, eyi ti Ben Enwonwu ya ni odun 1974 di ami isokan orilẹẹde Naijiria leyin ogun abele Biafra.
Olagunsoye Oyinlola: Kí Olorun dáríjì wá lórí ọ̀rọ̀ yíi, a ti kùnà ìlérí wa fún ìran Yorùb
Wọn lero wi pẹ isẹ ọna naa yoo mu ẹgbẹrun lona ọọdunrun poun wa, ti wọn ba lu ni gbanjo.
Eyi yoo jẹ owo to po ju ti ise ona igbalode lati owo omo orilẹẹde yi yoo pa .
Ben Okri, to je akowe ami ẹyẹ Booker ni ''isẹ ọna yi je ọkan gbogi ti wọn se awari rẹ ni bii aadota ọdun sẹyin''
Oríṣun àwòrán, Bonhams
Won yoo lu awon ise Ben Enwonu ni gbanjo ni Bonhams lojo kejidinlogbon osu keji ọdun 2018
O fi kun pe awari isẹ ọna naa ''pe fun ayo ati idunnu, igba iyipada lo si muba ise ona ''.
Ogbeni Enwonwu, ti opo eeyan ri gẹgẹ bi oludasile ise ọna igbalode lorilẹẹde Naijiria ya orisi meta eda aworan Tutu.
Oduduwa republic: Mo kọ̀ láti kópa nínú ìwọ́de Yoruba Nations rally ni Eko- Iba Gani Adams
Awọn awọran mẹta ohun di awati lẹyin iku rẹ lodun 1994.
Ko si ẹni to mo ibi ti awọn aworan meji toku wa.
- Buhari fẹ́ dá Naijiria padà sí ọdún 1984, ṣùgbọ́n a kò ní gbà fun- Femi Falana
- Ẹ wo ibi ọ̀rọ̀ dé dúró lórí àwọn afurasí tó lọ́wọ́ nínú ikú Tolulope Arotile
- Ọmọ ìyá kan náà mẹ́ta kú lẹ́yìn tí wọ́n jẹ Àmàlà ní Ilorin
- Àjọ̀dún odò Ẹ̀rìn, omi tí wọn kò gbọdọ̀ pa ẹja abàmì inú rẹ̀ wáyé nílùú Erinjiyan
- Ọwọ́ àjọ NDLEA tẹ ògbóǹtagì oníṣòwò òògùn olóró méje
- Olubunmi Afuye: Ohun táa mọ̀ nípa akọ̀ròyìn tó kàgbákò ikú lọ́wọ́ Adigunjalè tó fọ́ Báńkì l'Ondo
Ibeju Lekki Free Trade Zone: A ti bí ọmọ tó lọ Fásitì tí kò rí iná ọba rí- Olawale Eleto