Paedophile:Arákùnrin kan r'ẹ́wọ̀n ọdún mẹ́rìnlélógún he lórí ẹ̀sùn ìbálòpọ̀ pẹlú ọmọ ọjọ méjìlá

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Arakunrin ẹni ọdun mejidinlọgbọn kan to ba ọmọ ikoko ọjọ mejila lajọṣepọ ladajọ ti ran lẹwọn ọdun mẹrinlelogun.
Iṣẹlẹ ibalopo yi waye ni agbegbe Annalong ni County Down ni Ireland ni oṣu Kẹsan ọdun 2018.
Adajọ naa sọ pe awọn ko le darukọ ọdaran naa lati le fi daabọ bo ikoko naa amọ o juwe iwa yi gẹgẹ bi eleyi to buru gaan.
O tẹsiwaju pe idajọ ẹwọn ọdun mẹrinlelogun yi di dandan lati le fi ijiya to tọ jẹ arakunrin naa ki wọn si le fi daabo bo araalu.
- Wo ewu tó wà fún ìyálamọ tó ń jẹ olúbi ọmọ lẹ́yìn ọjọ́ ìkúnlẹ̀
- Ọlọ́pàá ti kó àwọn afurasí tí wọ́n bá òkú Demilade nínú 'cooler' nílé wọ́n ni Ekiti lọ sílé ẹjọ́
- Ṣọ̀ra! Ò leè kó sí pańpẹ́ ọlọ́pàá bí o bá na ọmọ rẹ - Ajàfẹ́tọ̀ ọmọdé
- Ọkùnrin kan pokùn so lẹ́yìn tó pàdánù N150,000 owó iléèṣẹ́ sórí tẹ́tẹ́
- Àwọn ọmọ ogun gba ọlọ́pàá 20 ti awọn agbésùmọ̀mi jí gbé
Wọn gbe ikoko yi lọ si ile iwosan Daisy Hill Hospital ni Newry nitori ifarapa si apa, ori, ẹgungun igbaya rẹ, ẹsẹ ati oju ara lọdun mẹta sẹyin.
Ọjọ mẹtala ni ọmọ naa lo ni ẹka pajawiri ile iwosan Royal Victoria to wa fun itọju awọn ọmọ ti ara wọn ko ba ya.
Ọjọ mẹsan ninu ọjọ mẹtala yi lo fi n gba afẹfẹ oxygen labẹ fẹntilatọ.
''Ẹjọ yi fọwọ kan ni lẹmi''
Esi iwadii kan tawọn oniṣẹ ilera gbe jade sọ pe ara ọmọ naa ti n ya ṣugbọn o wa ninu ewu pe o le ni aisan warapa .
Bẹẹ ni wọn s pe ọmọ naa le ni iṣoro kikọ ẹkọ tabi arun ọpọlọ lọjọ iwaju.
Nibẹrẹ ọdun yi lọdaran ẹni ọdun mejidinlọgbọn naa sọ niwaju adajọ pe oun jẹbi ibalopọ ati mimu inira ba ọmọ naa.
Ni ọjọ Ẹti ti adajọ gbe idajọ kalẹ o sọ pe arakunrin naa ko tiẹ ni itara iwa to buru jai to wu yi
Ìfipábánilòpọ̀: Abiamọ bú sẹ́kún nígbà tí ọkùnrin kan fi tipá bá ọmọ méjì lòpọ̀
O ni aile gbọ lẹkunrẹrẹ oun to ṣẹlẹ lati ẹnu ọdaran naa jẹ nkan to fọwọ kan ni lẹmi.
Adajọ Stephen Fowler QC sọ pe ọmọ ikoko ti ko le gba ara rẹ kalẹ ni ẹni ti o faragba iṣẹlẹ aburu yi.
''Diẹ lo ku ki ba ku bi kii ba ṣe ti itọju to ri gba.Yoo si pẹ gaan ki awọn ohun to rọ mọ iṣẹl yi to bẹrẹ si ni yọju sita.''
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Osun dóòlà ọmọ ọdún méje tí alágbàtọ́ rẹ̀ n fìyà jẹ
- Èèyàn méjì tó ṣẹ̀ṣẹ̀ gba Jesu gún pasítọ̀ ìjọ RCCG pa nínú ṣọ́ọ́ṣì l'Eko
- Rahmon Adedoyin ti sọ̀rọ̀ lórí àbájáde ìwádìí òkú ‘autopsy’ Timothy Adegoke tó kú sílé ìtura rẹ̀ nílé Ifẹ̀
- Ẹni bá rí i kó sọ o, Ìjọba ń wá ẹni dún 45 tó fipá bá ọmọ ọdún méje lòpọ̀
- Wo àwọn obìnrin kan tó ń fi ìbálòpọ̀ ṣe àlejò, tí wọn kìí sì wẹ̀
- 'Ìwẹ̀ mímọ́' rán Pásítọ̀ lọ́ sí ẹ̀wọ̀n ọdún mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n