Custom: Ọta ìbọn ba ẹnìkan nígbà tí àwọn òṣìṣẹ́ aṣọ́bodè àti ará ìlú kọjú ìjà síra wọn ní Yewa nípìnlẹ̀ Ogun

Oríṣun àwòrán, Premiumtimesng.com
Ọrọ di ẹni ori yọ, o di ile nilu Ayetoro, ijọba ibilẹ Ariwa Yewa nipinlẹ Ogun lalẹ ọjọ Ẹti, nigba ti awọn ara ilu naa ati awọn oṣiṣẹ ajọ aṣọbode kọju ija si ara wọn.
Awọn iwe iroyin abẹle sọ pe wahala na mu ki wọn o dana sun ọkọ ajọ aṣọbode mẹta, ti ibọn si tun ba ọdọ kan nilu naa.
Ẹnikan ti iṣẹlẹ naa ṣoju rẹ sọ fun awọn akọroyin pe ija naa bẹrẹ lẹyin ariyanjiyan kan to kọkọ waye laarin oṣiṣẹ aṣọbode kan ati araalu kan ti wọn lo jẹ afurasi onifayawọ.
- Ẹ̀yin aṣọ́bodè, ẹ yé ta ẹ̀jẹ̀ wa sílẹ̀ mọ́, agbègbè wa kìí ṣe ibùdó ogun - Olu ti Igboora
- ''Òsìsẹ́ Custom tó déédé sọ ara rẹ̀ di Ọ̀gá Àgbà CG ní ìdàmú ọpọlọ''
- Ilééṣẹ́ Aṣọ́bodè Naijiria n pa bílíọ̀nù N5.8 wọlé lójúmọ́ lẹ́yìn tíjọba ti ẹnu bodè -Ali
- Àwọn eèyàn kan fara gbọta níbi ìjà àwọn Aṣọ́bodè àti Ònífàyàwọ́ nígboro Iseyin lọ́jọ́ ọdún
- Wo ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa "food poisoning" àti bí o ṣe lè dẹ́kun rẹ̀
- Ẹ̀yin ọmọ Nàíjíríà, mó rí ìlàkàkà yín, ẹ ṣe sùúrù nítórí ìyá yìí yóò dópìn - Ààrẹ Buhari
Ọgbẹni Razak Adeyemi sọ fun awọn akọroyin pe 'wọn yanju ariyanjiyan naa, ti kaluku si ba tiẹ lọ'.
O ni lẹyin bi i wakati kan, ni ọkọ Hilux mẹrin, to kun fun awọn oṣiṣẹ aṣọbode, wọ ilu naa, ti awọn aṣọbode naa si bẹrẹ si ni yinbọn si inu afẹfẹ.
Asẹ́yìn, àwọn ẹbí olóògbé ṣì ń fomijé dárò àwọn tóṣìṣẹ́ 'Custom' yìnbọn pa nílùú Iseyin
Nkan ti awọn oṣiṣẹ aṣọbode naa ṣe la gbọ pe o bi awọn ọdọ ilu Ayetoro ninu, ti awọn naa fi kọju ija si wọn.
"Gbogbo igbiyanju lati da wọn lọwọ ibọn yinyin duro, lo jasi pabo. Niṣe ni wọn n yinbọn mọ awọn eeyan nigba ti awọn ọdọ koju wọn.".
Bethel Baptist high school Kaduna: Mi ò gbàgbọ́ pé ìjọba Naijiria ń ṣe ojúṣe rẹ̀ lórí ètò
Ẹlomiran to tun ba awọn akọroyin sọrọ, Ọgbẹni Nojeem sọ pe awọn oṣiṣẹ aṣọbode naa n yinbọn mọ awọn bi ẹni pe wọn paṣẹ fun wọn lati pa ilu naa run.
"Niṣe lo dabi i pe oju ogun la wa ni. Ti kii ba ṣe pe ọpọ awọn ọdọ wa ni ajẹsara, pupọ ni ko ba ti ku bayii."
Omi iké kan, l'èèyàn kan lè mu f'ọ́jọ́ mẹ́ta láì ro ti ekòló inú rẹ̀ - Ìlú Elega, Kwara
O ni ọpọ eeyan ni ọta ibọn awọn oṣiṣẹ aṣọbode ya aṣọ wọn pẹrẹpẹrẹ, ṣugbọn ọta ibọn ko raaye wọ inu agọ ara wọn, ayaafi ọmọkunrin kan ti wọn yinbọn mọ lẹẹmẹta."
A gbọ pe wọn ti gbe ọmọkunrin naa si ile itọju ibilẹ kan lati gba ẹmi rẹ la.
- Àwọn àgùnbánirọ̀ 25 lùgbàdì àrún Coronavirus ní ìpàgọ̀ NYSC
- Ta a ni ọ̀rẹ́ tóòtọ́, Ọba Buhari Oloto tó kú tó mú Ebenezer Obey wà nínú ìbànújẹ́?
- Ìdí rè é tí a ó fi gùnlẹ̀ ìyanṣẹ́lódí aláìlójọ́ káàkiri Naijiria - Ẹgbẹ́ Dokítà
- Èyí ni àlàyé lórí ètò ìsìnkú Tope AjogbaJesu àti ọjọ́ tí wọn yóò sin ín
- Ọ̀gá Àgbà Ọlọ́pàá, ẹ ríi dájú pé ẹ tú gbogbo àṣírí nípa ẹ̀sùn tí wọ́n fi kan Abba Kyari àti Hushpuppi - Àpapọ̀ Agbẹjọ́rọ̀
Iṣẹlẹ yii waye lẹyin ọjọ diẹ ti iru rẹ ṣẹlẹ ni Ibarapa nipinlẹ Ọyọ, eyi to mu ẹmi awọn eeyan kan lọ.
Gbajugbaja oṣere tiata, Bolaji Amusan fi hann wa bo se láyà to lori ètò ṣé o láyà.
Agbẹnusọ ajọ aṣọbode ni Area 1 Command nipinlẹ Ogun, Hammed Oloyede sọ fun awọn akọroyin pe iwadii ti bẹrẹ lori nkan to fa ija naa.
Iya Woli: Ẹ̀mí ìjókíjó, Wòó, Ṣọ̀kí, Wojú, Ṣàkùṣákù, One Corner...jáde!