Ogun: Ọkùnrín márùn ún fojúbalé ẹjọ́ lórí ẹ̀sùn ijà àti igbó fífà

Oríṣun àwòrán, Google
Ọkunrin marun un ti yọju si ileẹjọ ni ilu ọta, nipinlẹ Ogun lẹyin ti wọn fẹsun kan wọn pe wọn n lo oogun oloro ni gbangba.
Awọn ọkunrin marun un ọun ni Popoola Idris, 21; Efikioyha Tunwemi,26; Akanji Jimoh,30; Omodewu Monday,36 ati Akinwandi Nureni,28,amọ ti wọn ko fi adirẹsi wọn lede.
Ẹsun ti ileeṣẹ ọlọpaa fi kan wọn ni wi pe wọn n da igboro ru, ti wọn si n fa oogun oloro bii cannabis, indian hemp ni agbegbe Ijoko ni Ọta.
- Irọ́ ní o, a kò buwọ́lu Goodluck Jonathan fún ipò ààrẹ 2023 - APC
- Awakọ̀ ojú pópó láti Eko san N26,000 nítorí ó lu òfin tó de ìtànkálẹ̀ ààrùn Covid-19 - FRSC
- Ṣọun Ogbomọṣọ àti Sunday Dare gbóríyìn fún Buhari lórí 'Polytechnic' Ayede Ogbomoso
- Bàbá mi Ooni, ẹ foríjìn mí, ẹnu mi ò gbàá láti bú yín- Sunday Igboho tọrọ àforíjìn
Agbẹjọrọ ijọba, Emmanuel Adaraloye ni Ọjọ Kẹtadinlọgbọn , Oṣu Kini ni iṣẹlẹ ọun waye ni ilu Ọta, ti awọn ti wọn fẹsun kan naa si n ba ara wọn ja ni gbangba.
O fikun un wi pe iṣẹlẹ naa ti da rogbodiyan silẹ ni agbegbe ọun, ti awọn eniyan si n foya ni agbegbe ọhun.
World Cancer Day: Mo pàdánù ọkọ àti ọ̀rẹ́ bí mo ṣe ni 'Cancer'- Iwalade Adebimpe Adetunji
Bakan naa ni ileeṣẹ ọlọpaa ni wọn n da alaafia ilu ru, ti wọn si huwa to le fa ipaya ni agbegbe wọn.
Amọ, awọn ti wọn fẹsun kan naa ni awọn ko jẹbi ẹsun ti wọn fi kan awọn.
- Ènìyàn 1,138 tún ti lùgbàdì ààrùn Covid-19 ní Nàijíríà
- Inú mi kò bá dùn tí wọ́n bá le fi àwọn ọlọ́pàá tó lù mí jófin yàtọ̀ sí N5m tí wọ́n fẹ́ fún mi- Tola
- Àwọn ẹ̀gbọ́n mi ọkùnrin dá pín ogun bàbá wa, wọ́n ní pé obìnrin ni mí- Onyinye
- Àwọn aláìsàn ń padà lọ sílé lẹ́yìn tí àwọn Dókítà bẹ̀rẹ̀ ìyànṣẹ́lódì ní Ondo
Magisreti A. O Adeyemi wa gba beeli wọn ni iye owo ẹgbẹrun lọna aadọta naira, pẹlu oniduro kọọkan.
Adeyemi ni awọn oniduro wọn naa gbọgbọ ma a gbe ni ilu Ọta, ki wọn si ni iṣẹ lọwọ, eyi ti yoo fihan pe wọn n san owo ori wọn deede.
Ìtanijí lórí BBC Yorùbá: Odú Iwori Obara bá wa sọ̀rọ̀ lórí ìfaradà tó pọ̀
Ọ̀rọ̀ ìfẹ́ mú àgùnbánirọ̀ di èrò iléẹjọ́ ní ìpínlẹ̀ Kogi
Agunbanirọ kan ni ipinlẹ Kogi, Sam Abiola ti wa ni ile ẹjọ pẹlu arakunrin Adebiyi Sodiq, lẹyin ti wọn fẹsun kan pe o lu u ni jibiti ifẹ.
Oríṣun àwòrán, NYSC/TWITTER
Ni Ọjọ Aje ni wọn gbe awọn mejeeji lọ si ileẹjọ giga ni ipinlẹ Kwara to wa ni Ilorin lori ẹsun pe wọn lu obinrin ni jibiti ifẹ.
Ileeṣẹ ajọ to n gbogun ti iwa ibajẹ lorilẹ-ede Naijiria, EFCC ni ilu Ilorin lo gbẹ awọn mejeeji lọ si ileẹjọ lori ẹsun oniga mẹrin.
- Ọmọ ọdúnmẹ́tàdínlógún káwọ́ sẹ́yìn rojọ́ lórí ẹ̀sùn ìdúnkookò láti gbẹ̀mí ìyá rẹ̀''
- Seyi Makinde fi ọkọ̀ ńlá mẹ́rin dá ikọ̀ Amotẹkun lọ́lá nípìnlẹ̀ Oyo
- Mó wá sí ìpínlẹ̀ Ogun láti lé àwọn Fulani ajínigbé dànù lórí ilẹ̀ Yorùbá- Sunday Igboho
- Akomolede ati Asa Ondo: Wo ìdí tí Yorùbá ṣe ń lo Ìjàpá ni olú ẹ̀dá ìtàn Àlọ́ Àpagbé- Oyelowo Olufemi Lawrence
Awọn mejeeji ti wọn fi ẹsun kan naa jẹwọ pe lootọ ni awọn jẹbi ẹsun ti wọn fi kan awọn.
''Iwe ipẹjọ naa ni Sam Abiola sọ wi pe orukọ oun ni Missie Bonie lati fi parọ gba owo lọwọ ọrẹkunrin rẹ, Rick to si gba owo ni ọwọ rẹ.''
''Iye owo ti wọn si gba lọwọ rẹ jẹ $550, iye owo dọla ilẹ okeere, to si jẹ ki o ro wi pe, oun ni ifẹ rẹ denudenu.''
Akomolede ati Asa Ondo: Wo ìdí tí Yorùbá ṣe ń lo Ìjàpá ni olú ẹ̀dá ìtàn Àlọ́ Àpagbé- Oyelo
''Bakan naa ni Adebiyi Sodiq naa pe ara rẹ ni Maria ti to si tun pa irọ gba owo ni ọwọ arakunrin ọhun.''
''Eyi lodi si ofin orilẹ-ede Naijiria, ti iya si tọ si ẹnikẹni to ba ṣe gbajuẹ, to si tẹ oju ofin orilẹede Naijiria mọlẹ.''
- 'Ẹ yé bú Seyi Makinde, owó rẹ̀ ló fí ra Ọkọ bọ̀gìnì fún Alhaja Abosede Adedibu, Taye Currency, Mutiat Ladoja'
- Ènìyàn 676 tún ti lùgbàdì ààrùn Covid-19 ní Nàijíríà
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Eko ti f'òfin de ìpéjọpọ̀ tó bá ju àádọ́ta (50) èèyàn lọ torí ọwọ́jà kejì coronavirus
- Mínísítà ètò ìròyìn nígbà kan rí Tony Momoh dágbére fáyé lẹ́ni ọdún mọ́kànlélọ́gọ́rin
- Ó lódì sí òfin kí ilé ìtura fí 'camera' sí inú yàrá tí àwọn ènìyàn wà- Irukera FCCPC
- Gbajúgbajà akọrin jùjú, Shina Peters jẹ oyè Bíṣọ́ọ̀bù Ìjọ Cherubim àti Seraphim
- Gomina Seyi Makinde ṣe ìpàdé lóru mọ́jú pẹ̀lú àwọn eèyàn Ibarapa ní Oke Ogun
- A ti wọ́gilé àpèjẹ níbi ètò ìsìnkú àti ìgbéyàwó nítorí ìtànkálẹ̀ Covid 19 lẹ́ẹ̀kejì- Aarẹ Akufo Addo
- ''Ìjọba gbọ́dọ̀ fí òfin dé ìrìnàjò àwọn Fulani darandaran láti àríwá sí gúúsù Nàíjíríà''
Ninu idajọ rẹ, Adajọ Adenike Akinpẹlu ti sun igbẹjọ si Ọjọ Kọkanla, Osu Keji, ọdun 2019.